24/05/2026
*BIBA OLORUN PADE LOJOOJUMO (NBC YORUBA)*
*OSẸ KEJI-LE-LOGUN:*
*Sunday, May 31, 2026.*
*RIRU ARA-ẸNI SOKE.*
*Bibeli Kika: Heberu 10:22-25.*
*ẸSẸ LATI RANTI:* "Ẹ jẹ ki a yẹ ara wa wo lati rú ara wa si ifẹ ati si iṣẹ rere:" Heberu 10:24
*BIBA OLORUN PADE LOJOOJUMO (NBC YORUBA)*
*MONDAY, MAY 25, 2026*
*Ẹ JẸ KI A KỌRIN SI OLUWA*
*YBH 8: Ẹ Wọle F'Ọba*
1. Ewole f’ Oba, ologo julo,
E korin ipa ati ife Re;
Alabo wa ni, at’ Eni Igbani,
O ngbe ‘nu ogo, eleru ni iyin.
2. E so t’ ipa Re, e so t’ ore Re:
‘Mole l’ a*o Re gobi Re orun,
B’ ara ti nsan ni ‘keke, ibinu Re;
Ipa ona Re ni a ko si le mo.
3. Aiye yi pelu ekun re gbogbo,
Olorun, agbara Re l’ o da won:
O fi idi re mu ‘le, ko si le yi,
O si f’ okun se oja igbaiya re.
4. Itoju Re wa lara gbogbo won,
Ninu afefe, ninu imole;
Itoju Re wa ninu ‘ odo ti o nsan,
O si wa ninu iri ati ojo.
5. Awa erupe, aw’ alailera,
‘Wo l’ a gbekele, O ki o da ni;
Anu Re ronu, o si le de opin
Eleda, Alabo, Olugbala wa.
6. ‘Wo alagbara, onife julo,
B’ awon angeli ti yin O loke,
Be l’ awa eda Re niwon t’ a le se
A o ma juba Re, a o ma yin O.
*Ese Lati Ranti:* Ẹ wá, ẹ jẹ ki a kọrin si Oluwa: ẹ jẹ ki a hó iho ayọ si apata igbala wa. Orin Dafidi 95:1
*Bibeli Kika: Orin Dafidi 95:1-11*
[1] ẸWÁ, ẹ jẹ ki a kọrin si Oluwa: ẹ jẹ ki a hó iho ayọ̀ si apata igbala wa.
[2] Ẹ jẹ ki a fi ọpẹ wá si iwaju rẹ̀, ki a si fi orin mimọ́ hó iho ayọ̀ si ọdọ rẹ̀.
[3] Nitori Oluwa, Ọlọrun ti o tobi ni, ati Ọba ti o tobi jù gbogbo oriṣa lọ,
[4] Ni ikawọ ẹniti ibi ọgbun ilẹ wà: giga awọn òke nla ni tirẹ̀ pẹlu.
[5] Tirẹ̀ li okun, on li o si dá a: ọwọ rẹ̀ li o si dá iyangbẹ ilẹ.
[6] Ẹ wá, ẹ jẹ ki a wolẹ, ki a tẹriba: ẹ jẹ ki a kunlẹ niwaju Oluwa, Ẹlẹda wa.
[7] Nitori on li Ọlọrun wa; awa si li enia papa rẹ̀, ati agutan ọwọ rẹ̀. Loni bi ẹnyin o ba gbọ́ ohùn rẹ̀,
[8] Ẹ má sé aiya nyin le, bi ti Meriba ati bi ọjọ na ni Massa, li aginju.
[9] Nigbati awọn baba nyin dan mi wò, ti nwọn wadi mi, ti nwọn si ri iṣẹ mi.
[10] Ogoji-ọdun tọ̀tọ ni inu mi fi bajẹ si iran na, mo ni, Enia ti o ṣina li aiya ni nwọn, nwọn kò si mọ̀ ọ̀na mi:
[11] Awọn ẹniti mo si bura fun ni ibinu mi pe, nwọn ki yio wọ ibi isimi mi.
________
D.A. Carson wi pe "Ijosin jẹ ọna ti o tọ lati kọ iha ti o tọ si gbogbo didara Ọlọrun, ki a fi gbogbo ọla ti o tọ ati eyi ti o yẹ fun Ẹlẹdaa wọn—Ọlọrun, nitori pe Oun ni o tọ si."
Ijosin kii kan ṣe eto to ti di baraku, ṣugbọn o jẹ iwoye ti a ni nipa ibasẹpọ wa pẹlu Ọlọrun.
Ninu ẹṣẹ Bibeli ti oni, Dafidi Ọba mọnu ba iṣẹ-pataki ijosin tootọ. Onisaamu yii n pe wa lati darapọ ninu fifi ayọ yin Ọlọrun.
Ipe yii pin si oriṣii ọna: akọkọ jẹ ipe lati kọrin, ho ati lati wọle niwaju Oluwa, ki a mọ riri ọlanla, iṣẹda ati irapada Rẹ.
Ọna keji jẹ ikilọ lati mase ṣe aya le, ki a ma si ṣe ọtẹ, gẹgẹ bi o ṣe tọka si iriri awọn ọmọ Isrẹli ni aginjù.
Ijosin maa n gbe wa kuro ni agbegbe ti a wa lọ si ibomiran lati ni imọlara ifarakinra pẹlu Ọlọrun bi a ba ṣe e bi o ti yẹ.
Nitori naa, o gbọdọ fi gbogbo ọkan rẹ jọsin, ki o fi ẹmi imoore ati iyin jọba han.
Nígba ti o ba n darapọ mọ awọn miiran lati jọsin, o n ro idapọ ati iṣọkan lagbara, o si n kede yiye Ọlọrun fun araye.
Ṣe amulo otitọ yii nipa siso ijosin tootọ di ọna igbe-aye rẹ, maa bu ọla fun Ọlọrun ni gbogbo agbọn aye rẹ, ki o si maa mu ibasẹpọ ti o nitumọ dagba pẹlu awọn onigbagbọ akẹgbẹ rẹ nipasẹ ṣiṣe alabaapin awọn iriri ijosin papọ.
*Ọrọ Ọgbọn:* Ọlọrun ni inu-didun ninu ijosin awọn ọmọ Rẹ.
*Ọrọ fun Ironu:* Njẹ o jẹ olujọsin tootọ si Ọlọrun?
*Iṣẹ Ṣiṣe:* Fi awọn orin tuntun jọsin si Ọlọrun loni.
*Adura:* Oluwa Ọlọrun, mo yin Ọ fun ẹni ti O jẹ si mi ati ibikitá Rẹ lori emi ati idile mi. Jẹ ki orukọ Rẹ di ayinlogo t**i lae.
*Adura:* Oluwa, ma jẹ ki n dun ara mi ni awọn anfaani ti mo ni ninu Rẹ.
*Gbadura fun awọn Ẹni-ọwọ wọnni, idile, ati awọn ọmọ ijọ Ọlọrun:*
Ruth Odejayi, Ibadan; Sunday Auta, Fadama; Deborah N. Adedọja, Kaduna; Joel O. Odesọji, Ogijo; Dada Ajibọla, Eko; Adeoye Isaac, Ogun; Daniel M. Kashama, Uragi; Adisa L. Adedoyin, Ogbooro; Olatubọsun A. Gbenga, Ṣaki; Adedara V. Adeoye, Abidjan; Michael A. Oguntoye, Oṣogbo; Ọlayinka S. Ọlatunji, Eko; Oyunniyi A. Philip, Ogun; P. I. Bangbose, Ogun; Daniel V. Francis, Ang. Habu; Adeṣọla P. Adeọla, Rivers; Prince U. F. Ihedike, Rivers; Peter O. Siyanbọla, Ibadan; Kehinde Rotimi, Kogi; S. A. Asamu, Ogbomọṣọ; Oyekunle Ebenezer, Ogbomọṣọ; Wọle Ajao, Ogbomọṣọ; Isaac A., Ogbomọṣọ; Iyanda S. Imọlẹ, Ogbomọṣọ; Ajala John Eku; Oleahbie Paul A., Edo; Felicia E. Odjesawha, Ughelli; Ayankanmi J. Temitọpẹ, Ilọra; A. E. Ọladẹlẹ, Ọyọ; Oyelaran O. K. Michael, Ẹdẹ; Ọparinde Matthew O., Ẹdẹ; Ogunlola S. Olatunji, Yobe; Edward K. Afọlabi, Ibadan; Simon D. Kdrau, Malaki; Victor Sako, Huri; Caleb B. Sodangi, Bẹgẹ; Rufai Ishaya, Malumfashi; Jesulọwọ O. Emmanuel, Ẹlẹyin.
*KBJL: Esteri 1-5*