26/05/2026
ỌJỌ́ RÚ (WEDNESDAY), 27 MAY, 2026
Kíkọ Nínú Ìwé Orin ECWA: EHB 459
IBI KÍKÀ: EFESU 6:10 – 20
KÓKÓ ẸKỌ: GBÁRADÌ FÚN OGUN
EFESU 6:10 – 20
10 Lakotan, ará mi, ẹ jẹ alagbara ninu Oluwa, ati ninu agbara ipá rẹ̀.
11 Ẹ gbe gbogbo ihamọra Ọlọrun wọ̀, ki ẹnyin ki o le kọ oju ija si arekereke Eṣu.
12 Nitoripe kì iṣe ẹ̀jẹ ati ẹran-ara li awa mba jijakadi, ṣugbọn awọn ijoye, awọn ọlọla, awọn alaṣẹ ibi òkunkun aiye yi, ati awọn ẹmí buburu ni oju ọrun.
13 Nitorina ẹ gbe gbogbo ihamọra Ọlọrun wọ̀ ki ẹnyin ki o le duro tiri si ọjọ ibi, nigbati ẹnyin bá si ti ṣe ohun gbogbo tan, ki ẹ si duro.
14 Ẹ duro nitorina lẹhin ti ẹ ti fi àmure otitọ di ẹgbẹ nyin, ti ẹ si ti di ìgbaiya ododo nì mọra;
15 Ti ẹ si ti fi imura ihinrere alafia wọ̀ ẹsẹ nyin ni bàta;
16 Léke gbogbo rẹ̀, ẹ mu apata igbagbọ́, nipa eyiti ẹnyin ó le mã fi paná gbogbo ọfa iná ẹni ibi nì.
17 Ki ẹ si mu aṣibori igbala, ati idà Ẹmí, ti iṣe ọ̀rọ Ọlọrun:
18 Pẹlu gbogbo adura ati ẹbẹ ni ki ẹ mã gbadura nigbagbogbo ninu Ẹmí, ki ẹ si mã ṣọra si i ninu iduroṣinṣin gbogbo, ati ẹ̀bẹ fun gbogbo enia mimọ́;
19 Ati fun mi, ki a le fi ohùn fun mi, ki emi ki o le mã fi igboiya yà ẹnu mi, lati mã fi ohun ijinlẹ ihinrere hàn,
20 Nitori eyiti emi jẹ ikọ̀ ninu ẹ̀wọn: ki emi ki o le mã fi igboiya sọ̀rọ ninu rẹ̀, gẹgẹ bi o ti tọ́ fun mi lati mã sọ.
GBÁRADÌ FÚN OGUN
Ìgbé ayé Kristẹni kì í se “ayé ìgbádùn”, Ẹkọ́ kíkà t’òní tako ọ̀rọ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀kọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí kò lọ déédé.
Paulu sí aṣọ lójú ọ̀rọ̀ yìí pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ tó lágbára tí ó tako àṣẹ ológun kan nígbà tí ó sọ fún àwọn ará Éfésù, “Lákótán, ará mi, ẹ jẹ́ alágbára nínú Olúwa àti nínú agbára ipá Rẹ́”.
Ohun rere nipa ìtọ́nisọ́na yìí ni pé gbogbo Onígbàgbọ́ nílò láti dojúkọ ogun yìí ní gbogbo wọn pèsè fún nínú Olúwa, nítorí ogun yìí “Nítorí kì í se ẹran ara àti ẹ̀jẹ̀ ni àwa ń bá ja ìjàkadì sùgbọ́n àwọn ìjòyè, àwọn ọlọ́la, àwọn aláṣẹ ibi òkùnkùn ayé yìí, àti àwọn ẹ̀mí búburú ní ojú ọ̀run” (ẹsẹ 12).
A ń dojúkọ àwọn agbára òkùnkùn tí ó wà lábẹ́ ìsàkóso Sàtánì, àti pé ohun ìjà kan ṣoṣo tí a le lò takò ò ní “gbogbo ìhámọ́ra Ọlọ́run” pẹ̀lú àmùrè òtítọ́, ìgbayà òdodo, ìmúra ìhìnrere àlàáfíà, àpátà ìgbàgbó, àsíborí ìgbàlà, àti idà ẹ̀mí, àti gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀.
O kò le máa gbé ìgbé ayé ẹrú tàbí ìsẹ́gun lọ́wọ́ èsù nítorí ó ńi ohun gbogbo tí ó nílò fún ìgbé ayé ìsẹ́gun Onígbàgbọ́.
IBÉÈRÈ :
Ǹjẹ́ ìwọ ń gbé ìgbé ayé asẹ́gun lóri Sátánì àti àwọn ẹ̀mí òkùnkùn, tàbí ò ń gbé lábẹ́ àkóso rẹ?
ÀDÚRÀ :
Olúwa, ràn mí lọ́wọ́ láti gbé ayé mi lójoojúmọ́ dáradára pẹ̀lú gbogbo ìhámọ́ra Rẹ, ní orúkọ Jésù, Àmín.
OÚNJẸ ÒÒJỌ́ - 2026.