Bttop Media "Epada si oju ona igbaani"

Bttop Media "Epada si oju ona igbaani" A se agbekale ojulowo eko oro Olorun yi ni ede Yoruba fun anfani gbogbo eniyan papa julo fun awa ti aje kristeni.

GẸGẸ BI KRISTIANI N JẸ JESU PAWÁ L'ÁSẸ LATI KORIRA ÀWỌN ẸBÍ WA? GẸ́GẸ́ BÍ A TI RI BI ÀWỌN ẸLẸ́SÌN KAN SE N TU ÌWÉ LUKU 1...
28/08/2026

GẸGẸ BI KRISTIANI N JẸ JESU PAWÁ L'ÁSẸ LATI KORIRA ÀWỌN ẸBÍ WA? GẸ́GẸ́ BÍ A TI RI BI ÀWỌN ẸLẸ́SÌN KAN SE N TU ÌWÉ
LUKU 14:26 SI BI WỌN TI FẸ́.
Ọ̀RỌ̀ ti Jesu sọ ninu iwe Lúùkù 14:26, jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọ̀rọ̀ tó le láti lóye, ki ise ọrọ ti a le fi ọgbọn ori eniyan loye rẹ, bikose nipa iranlọwọ Ẹmi-mimo ni a fi le mọ ohun ti Jesu n wi gan ni pato ninu ẹsẹ ọrọ Ọlọrun naa.

Jesu wípé.
“Bi ẹnikan ba tọ̀ mi wá, ti ko si korira baba rẹ̀, ati iya, ati aya, ati ọmọ, ati arakunrin, ati arabinrin, ani ati ẹmí ara rẹ̀ pẹlu, kò le ṣe ọmọ-ẹhin mi.” — Lúùkù 14:26

Kinni ọrọ yi túmọsi':
1. Ọrọ ti Jésù sọ yi ko túmọ̀ sí pé kí ọmọ-ẹ̀yìn Kristi máa kórìíra àwọn òbí, aya, ọkọ, ọmọ tàbí àwọn arákùnrin rẹ̀. Bíbélì fúnra rẹ̀ kọ́ wa pé kí a nífẹ̀ẹ́ àwọn ènìyàn, kí a sì bọ̀wọ̀ fún àwọn òbí wa.
2. Ọ̀rọ̀ “kórìíra” níbí ń tọ́ka sí fífẹ́ Jésù ju gbogbo ohun kohun lọ, títí débi pé ìfẹ́ wa sí àwọn ẹbí wa kò gbọdọ̀ ju ìfẹ́ àti ìgbọràn wa sí Kristi lọ.

Kí ni Jésù n sọ gan?
1. Kristi gbọdọ̀ jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ nínú ìgbé ayé wa:
Bí a bá ní láti yan láàárín ìgbọràn sí Kristi àti ohun tí ẹbí wa fẹ́ tí ó tako Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, Kristi ni a gbọdọ yan.
2. Kò yẹ kí ẹbí di ohun tí ó ń dí wa lọ́wọ́ láti tẹ̀lé Jésù:
Nígbà míì, ẹbí lè má gba bi awa ti gbàgbọ́, tàbí iṣẹ́ ìránṣẹ́ wa. Ṣùgbọ́n a ko gbọdọ fi Kristi silẹ nítorí pe a fẹ tẹ awọn ẹbi wa lọrùn.
3. “Ani àti ẹ̀mí ara rẹ̀ pẹlu”: Eyi túmọ̀ sí pé a gbọdọ̀ fi ara wa àti àwọn ìfẹ́ tiwa sí abẹ́ ìjọba Kristi.
Kì í ṣe ohun gbogbo tí a fẹ́ ni a le e se; a gbọdọ̀ sẹ ara wa láti tẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run.
4. Ó jẹ́ owo idiyelé tí ọmọ-ẹ̀yìn Kristi gbọ́dọ̀ san:
Jésù ń sọ fún àwọn tí wọ́n fẹ́ tẹ̀lé e pé ọmọ-ẹ̀yìn tòótọ́ gbọdọ̀ le ṣetan láti fi ohun gbogbo sílẹ̀ nítorí Kristi ati Ìjọba Ọlọrun.

Ọrọ ti Jesu sọ ni Lúùkù 14:26 tún ba ohun tí Jésù tún sọ ní Mátíù 10:37 mu ti o wipe' "Ẹniti o ba fẹ baba tabi iya jù mi lọ, kò yẹ ni temi: ẹniti o ba si fẹ ọmọkunrin tabi ọmọbinrin jù mi lọ, kò si yẹ ni temi".

Ní ṣókí.
Lúùkù 14:26 kò kọ́ wa láti kórìíra ẹbí wa; ó kọ́ wa pé ìfẹ́ àti ìgbọràn wa sí Kristi gbọdọ̀ ga ju ìfẹ́ wa sí ẹnikẹ́ni lọ. Ọmọ-ẹ̀yìn Kristi tòótọ́ ni ẹni tí ó sọ pé, “Kristi ni mo máa tẹ̀lé, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó lè ná mi ní ohun tí mo fẹ́ràn jù lọ.”

------------------------------------
Awọn Audio ẹkọ ọrọ Ọlọrun wa nilẹ fún gbogbo awa ọmọ Ọlọrun ti a ba fẹ, nitorina ẹdarapo mọ WhatsApp group ẹkọ Bibeli fun gbogbo ọmọ Ọlọrun ti o nifẹ si ojúlówó ẹkọ ọrọ Ọlọrun bi ti igbaani pẹlu Whatsapp link yi:
👇👇👇
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw?s=cl&p=a&ilr=4

04-08-2026.
+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

21/08/2026

SE LUKU WA LÁRA ÀWỌN ỌMỌ ẸHÌN TÍ O BA JESU RÌN NÍ ÌGBÀ AYÉ JESU?

(Ibeere láti ọdọ Arabinrin Grace Omosalewa).

IDAHUN SI IBEERE.
Bíbélì kò fi hàn pé Luku jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tó bá Jésù rìn nígbà iṣẹ́ iransẹ Jesu lórí ilẹ̀ ayé.
- Luku kò mẹ́nu ba ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí ti ori Jesu ni ojukoju ninu iwe Luku ti o kọ. Dípò bẹ́ẹ̀, ó sọ wípé" Ohun gba awọn ọrọ ti oun kọ sinu iwe naa lati pàṣẹ àwọn enia ti wọn dawọle e lati tò ìhin wọnni jọ lẹsẹsẹ, iyẹ awọn ti ọrọ nipa ise-iranse Jesu se ojú wọn.
(Luku 1:1–4). Eyi ń fi hàn pé" Luku kọ iwe Luku láti inú ẹ̀rí àwọn ọmọ ẹhìn ti wọn ba Jesu rin ni ìgbà Ayé Rẹ.

- Ọ̀pọ̀ àwọn onímọ̀ bíbélì dá Luku mọ̀ gẹgẹ bí ọ̀rẹ́ àti alábàákẹ́gbẹ́ Pọ́ọ̀lù, tí a pè ní “oníṣègùn olùfẹ́” (Kólósè 4:14; Fílémónì 24; 2Tímótì 4:11). Nítorí náà, ó ṣeé ṣe kí Luku darapọ̀ mọ́ ìgbàgbọ́ Kristẹni lẹ́yìn ikú àti àjíǹde Jésù, kì í ṣe pé ó wà lára àwọn méjìlá tàbí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tó ń tẹ̀lé Jésù nígbà Ayé rẹ̀.

Ní ṣókí: Luku jẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ àti akọ̀wé Ìhìn Rere, àti alábàákẹ́gbẹ́ Pọ́ọ̀lù; kò sí ẹ̀rí tó dájú pé ó bá Jésù rìn nígba akoko ise-iranse Rẹ.

Edarapọ mọ ise-iranse yi ni ori WhatsApp fún àwọn audio ẹkọ ọrọ Ọlọrun.

https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw?s=cl&p=a&ilr=4

BTTOP MEDIA

+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo

ORIṢI AWỌN ỌNA MÉJÌ TI EPISTELI PIN SI.1. EPISTELI TI A  KỌ SÍ AWỌN ÌJỌ (CHURCH EPISTLES): Ni awọn lẹ́tà tí a kọ sí ìjọ ...
19/08/2026

ORIṢI AWỌN ỌNA MÉJÌ TI EPISTELI PIN SI.

1. EPISTELI TI A KỌ SÍ AWỌN ÌJỌ (CHURCH EPISTLES):
Ni awọn lẹ́tà tí a kọ sí ìjọ kan tàbí sí àwọn Kristẹni kan ní pàtó, nítorí ìṣòro, ẹ̀kọ́, ìwà, tàbí ìbéèrè kan tí wọ́n ní.
Àpẹẹrẹ:
- Róòmù — sí àwọn Kristẹni tó wà ní Róòmù.
- 1Kọ́ríńtì àti 2Kọ́ríńtì — sí ìjọ Kọ́ríńtì.
- Gálátíà — sí ìjọ Gálátíà.
- Éfésù — sí ìjọ Éfésù.
- Fílípì — sí ìjọ Fílípì.
- Kólósè — sí ìjọ Kólósè.
- 1Tẹsalonika àti 2Tẹsaloníka — sí ìjọ Tẹsalóníkà.
Nítorí náà, àfojúsùn wọn jẹ́ pàtó sí ìjọ tàbí ẹgbẹ́ kan.

2. EPISTELI TÍ A KỌ SÍ AWỌN ENIYAN KAN NI PÀTÓ (GENERAL EPISTLES):
Àwọn Episteli wọ̀nyí kò dá lórí ìjọ kan, ṣugbọn a kọ́ wọn si àwọn Kristẹni kan ni, tàbí sí àwọn onígbàgbọ́ ní oríṣìíríṣìí ibi.
Fún àpẹrẹ:
Àwọn èyí ni awọn Episteli ti a kọ sí àwọn ènìyàn
(General Epistles) ni:
- Jákọ́bù
- 1Pétérù
- 2Pétérù
- 1Jòhánù
- 2Jòhánù
- 3Jòhánù
- Juda.
- 1Timoteu
- 2Timoteu
- Titu
- Filemoni.

AWỌN OLUGBA AWỌN IWE EPISTELI TI A KỌ SI AWỌN ENIYAN KAN NI PÀTÓ
(GENERAL EPISTLES).
- Iwe Jákọ́bù:
Awọn olugba iwe naa ni awọn ẹ̀yà méjìlá tí a tú ká kiri.” Jak 1:1.
- 1Pétérù àti 2Pétérù:
Àwọn Kristẹni tí wọ́n tú ká ní Pọ́ńtù, Gálátíà, Kappadókíà, Asia àti Bítíníà ni a kọ wọn sí.
- 1Jòhánù:
Awọn ọmọ Johannu nínú Oluwa ni awọn olugba ìwé náà. 1John 2:1.
- 2Jòhánù:
Obìnrin ọlọlá kan àti àwọn ọmọ rẹ ni olugba iwe naa.
2John 1:1.
- 3Jòhánù:
Alagba (Elder) Gaiu ni olugba iwe na.
3John 1:1.
- Juda:
Awọn ti Olorun pe ni awọn olugba iwe na. Juda 1.
- 1Timoteu ati 2Timoteu:
Timoteu ọmọ Paulu nínú ẹmi ni awọn olugba ìwé méjèèjì na.
- Titu:
Titu alaba ṣiṣẹ pọ Paulu ni olugba iwe na.
- Filemoni:
Fílémónì, Kristẹni kan tí Paulu mọ̀ dáadáa ni, olugba iwe na.....................................................
Ẹfi comment s'ọwọ si isalẹ Post yi pe'
"ỌRỌ ỌLỌRUN YE"...............................................
Edarapọ mọ WhatsApp group ẹkọ bíbélì pẹlú WhatsApp link tàbí number yi:
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw?s=cl&p=a&ilr=4

+2348124147703
BTTOP MEDIA
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

ÀWỌN LẸ́TÀ PỌ́Ọ̀LÙ ÀTI BÍ WỌ́N SE DI APÁ KAN ÌWÉ NÍNÚ BÍBÉLÌ.Àwọn Ìwé Pọ́ọ̀lù ni àwọn lẹ́tà tí Pọ́ọ̀lù kọ sí àwọn ìjọ àt...
16/08/2026

ÀWỌN LẸ́TÀ PỌ́Ọ̀LÙ ÀTI BÍ WỌ́N SE DI APÁ KAN ÌWÉ NÍNÚ BÍBÉLÌ.

Àwọn Ìwé Pọ́ọ̀lù ni àwọn lẹ́tà tí Pọ́ọ̀lù kọ sí àwọn ìjọ àti àwọn Kristẹni kan láti kọ́ wọn, láti fún wọn ní ìmọ̀, láti tún wọn ṣe nínú ìgbàgbọ, àti láti fún wọn ní ọrọ ireti nínú ìgbàgbọ́ wọn.

1. AWỌN LẸ́TÀ TÍ PỌ́Ọ̀LÙ KỌ:
Ninu ẹkọ Kristẹni, awọn lẹ́tà mẹ́tàlá ni a mọ̀ sí Àwọn Lẹ́tà Pọ́ọ̀lù. Awọn lẹta na niyi:
1. Róòmù
2. 1Kọ́ríńtì
3. 2Kọ́ríńtì
4. Gálátíà
5. Éfésù
6. Fílípì
7. Kólósè
8. 1Tẹsalóníkà
9. 2Tẹsalóníkà
10. 1Tímótì
11. 2Tímótì
12. Títù
13. Fílémónì
A tún máa ń pè àwọn mẹ́ta ninu awọn lẹta naa ni, awọn Lẹ́tà Olùṣọ́-àgùtàn (Pastoral Epistles) nítorí pé wọ́n ní àwọn ìtọ́ni pàtàkì fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ àti ìṣàkóso ìjọ.
Awọn lẹta mẹtẹta naa ni:
- 1Tímótì,
- 2Tímótì àti
- Títù

2. KÍ NI ÌDÍ TÍ PỌ́Ọ̀LÙ FI KỌ ÀWỌN LẸ́TÀ WỌ̀NYÍ?
Pọ́ọ̀lù kò kọ àwọn lẹ́tà náà fún ìdárayá. Ṣugbọn o kọ́ awọn ìwé yi nítorí ki awọn ọmọ Ọlọrun ti o wa nínú àwọn Ìjọ wọnyi, ki wọn le fi ẹsẹ munlẹ ninu igbagbọ ki wọn si le ma gbe igbe aye iwa mimọ.

OHUN TÍ AWỌN ẸKỌ PAULU DALE LORI NÍNÚ AWỌN ÌWÉ YI:
- O kọ wọn nípa ìgbàlà àti ìgbàgbọ́ nínú Jésù Kírísítì.
- O ṣàlàyé ẹ̀kọ́ Kristẹni.
- O kìlọ̀ fún wọn lórí ẹ̀kọ́ èké.
- O kọ wọn bi a ti le wa ojutu si awọn isoro Ìjọ.
- O kọ́ wọn nípa àwọn ìwà tí ó yẹ fún Kristẹni.
- O sọ ọrọ iwuri fún wọn, O si gb'awọn níyànjú.
- O kọ́ wọn nípa bí àwọn ọmọ Ọlọ́run ṣe yẹ kí wọ́n máa gbé.
- O kọ wọn nipa awọn ẹbun ẹmi ati eso ẹmi.
- O kọ wọn nipa ohun ti Emimọ jẹ.
- O kọ wọn nipa Ìgbàlà nípasẹ̀ ìgbàgbọ́ nínú Jésù Kírísítì Róòmù 3:23-24.
- O kọ wọn nipa Ìyè tuntun nínú Kírísítì — 2 Kọ́ríńtì 5:17.
- O kọ wọn nipa Ìfẹ́ àti ìwà Kristẹni 1Kọ́ríńtì 13.
- O kọ wọn nipa ìṣọ̀kan ara Kírísítì Éfésù 4:1-6.
- O kọ wọn ni iwà ìrẹ̀lẹ̀ biti Kírísítì Fílípì 2:5-11.
- O kọ wọn nipa ìdúróṣinṣin nínú ìgbàgbọ́ 2Tímótì 4:7.

3. BÁWO NI ÀWỌN LẸ́TÀ RẸ
WỌ̀NYÍ SE DI APÁ KAN ÌWÉ NÍNÚ BÍBÉLÌ?
Ó ṣe pàtàkì láti jẹ ki a mọ̀ pé Pọ́ọ̀lù kọ ni o sọ àwọn lẹ́tà rẹ̀ fúnra rẹ̀ di Bíbélì. Àwọn lẹ́tà náà kọ́kọ́ jẹ́ àwọn ìwé tí a kọ sí àwọn ìjọ àti àwọn ènìyàn kan.
Àwọn ìjọ àkọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ sí í ka, pa mọ́, pín, àti lo àwọn lẹ́tà wọ̀nyí nínú ẹ̀kọ́ àti ìjọsìn. Bí àpẹẹrẹ, Pétérù sọ nípa àwọn ìwé Pọ́ọ̀lù pé:
“...gẹ́gẹ́ bí arákùnrin wa olùfẹ́ Pọ́ọ̀lù pẹ̀lú ọgbọ́n tí a fi fún un, o n sọrọ awọn n kan wọnyi nínú iwe rẹ gbogbo......"
2Pétérù 3:15-16
Ẹsẹ̀ yìí ṣe pàtàkì gan-an nítorí pé ó fi hàn pé àwọn ìwé Pọ́ọ̀lù ti ń kaakiri láàárín àwọn Kristẹni, tí wọ́n sì ń ka wọn sí àwọn ìwé pàtàkì fún ẹ̀kọ́.

4. ITẸWỌGBA AWỌN ÌWÉ NAA.
Itẹ́wọ́gbà túmọ̀ sí pé àwọn ìjọ mọ̀ pé àwọn ìwé kan yẹ kí wọ́n jẹ́ apá inú Ìwé Mímọ́, tí wọ́n sì gba àṣẹ àti ìkọ́ni wọn gẹ́gẹ́ bí apá kan nínú Bíbélì.
A kò gbà àwọn lẹ́tà Pọ́ọ̀lù nítorí pé Pọ́ọ̀lù jẹ́ olókìkí nìkan. Dípò bẹ́ẹ̀, àwọn Kristẹni àkọ́kọ́ wo ohun tí àwọn lẹ́tà náà ń kọ́, ìbáṣepọ̀ wọn pẹ̀lú ìgbàgbọ́ àwọn Àpọ́sítélì, àti bí àwọn ìjọ ṣe ń gba wọ́n.
"Gbogbo iwe-mimọ́ ti o ni imísi Ọlọrun li o si ni ère fun ẹkọ́, fun ibani-wi, fun itọ́ni, fun ikọ́ni ti o wà ninu ododo" 2Tímótì 3:16.

IPARI.
Nítorí náà, Àwọn Ìwé/Lẹ́tà Pọ́ọ̀lù jẹ́ apá pàtàkì nínú Majẹ̀mú Tuntun. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn lẹ́tà tí Pọ́ọ̀lù kọ sí àwọn ìjọ àti àwọn onígbàgbọ́, ṣùgbọ́n àwọn ìjọ àkọ́kọ́ ń ka wọ́n, wọn ń pín wọn, wọn n kọ́ àwọn ènìyàn láti inú wọn, àti pé wọ́n mọ̀ pé ẹ̀kọ́ inú àwọn ìwé na bá ìgbàgbọ́ àwọn Àpọ́sítélì mu. Nípasẹ̀ ìlànà ìdánimọ̀ àti ìtẹ́wọ́gbà ìwé mímọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ ní ìgbà ìjọ àkọ́kọ́, àwọn lẹ́tà wọ̀nyí di apá kan nínú Canon ti Majẹ̀mú Tuntun tí àwọn Kristẹni ń lò títí di òní.
-----------------------------------------------------------------------
✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️
Efi comment yin s'ọwọ si abẹ ẹkọ yi fun ibeere, tabi ọrọ ìmọ riri.
-----------------------------------------------------------------------
Anfani wa fun yin lati darapọ̀ mọ WhatsApp group ile ise-iranse yi nibiti ẹ o ti ma gba awọn audio ẹkọ ti o wa lati ile ise-iranse yi ni ọfẹ.
Edarapọ pẹlu WhatsApp link 🔗 yi.
👇👇👇
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw
-----------------------------------------------------------------------
+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

WhatsApp Group Invite

KINNI IDITI JESU FI RÁN ÀWỌN ỌMỌ ẸHÌN RẸ LÁTI WÀÁSÙ IHINRERE FÚN AWỌN ENIYAN ISRAẸLI NÌKAN, TI KO SI RAN WỌN SI GBOGBO A...
07/08/2026

KINNI IDITI JESU FI RÁN ÀWỌN ỌMỌ ẸHÌN RẸ LÁTI WÀÁSÙ IHINRERE FÚN AWỌN ENIYAN ISRAẸLI NÌKAN, TI KO SI RAN WỌN SI GBOGBO AYE NI AKOKO NA. SUGBON LẸYÌN AJINDE RẸ̀ TI O SẸ̀SẸ̀ WÁ RAN WỌN SÍ GBOGBO AYÉ?

Ìbéèrè yìí dára gan-an. Kò sí àtakò láàárín Matiu 10:5–6 àti Ìṣe Àwọn Aposteli 1:8. Dípò bẹ́ẹ̀, ó fi hàn pé ètò Ọlọ́run ń tẹ ṣí síwájú ní sisẹ n tẹle ni.

1. Ní ìbẹ̀rẹ̀, Jesu rán wọn sí àwọn Àgùntàn Israẹli ti o sọnù nìkan (Matiu 10:5–6):
Nígbà tí Jesu ń bẹ láyé, iṣẹ́ Rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli nítorí pé àwọ́n ni àwọn ènìyàn májẹ̀mú Ọlọ́run:
- Awọ́n ni a kọ́kọ́ fún ní òfin àti àwọn wòlí.
- Awọn ni Ọlọ́run ti se ìlérí Mèsáyà fún.
Nítorí náà, awọn ni ó yẹ kí wọ́n kọ́kọ́ gbọ́ ìròyìn ihinrere náà.
Jesu fúnra Rẹ̀ sọ wipé:
"A kò rán mi bí kò ṣe sí àwọn àgùntàn ilé Israẹli ti o sọnù." (Matiu 15:24)
Àti pé:
"Ìhìnrere ni a ó kọ́kọ́ wàásù fún àwọn Júù." (Romu 1:16)

2. Lẹ́yìn ikú àti àjíǹde Jesu, iṣẹ́ náà takọsọ sí gbogbo ayé:
Lẹ́yìn tí Jesu kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ayé, tí Ó sì jí dìde, ìgbàlà ki i se ti Israẹli nìkan mọ́. Ó ti di ti gbogbo ènìyàn.
Nítorí náà, Jesu sọpé:
- "Ẹ lọ, Ẹ ma kọ Orílẹ̀-èdè gbogbo." (Matiu 28:19).
- "Ẹ ó sì ma se ẹlẹ́rìí mi... títí dé òpin ilẹ̀ ayé." (Ìṣe 1:8).

3. Kí ló fa ìyípadà náà?:
- Jesu ti parí iṣẹ́ ìràpadà Rẹ̀ lórí agbelebu (Johanu 19:30):
- Májẹ̀mú tuntun ti bẹ̀rẹ̀ nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ Kristi (Luku 22:20; Heberu 9:15).
- Ẹ̀mí Mímọ́ ti sọ̀kalẹ̀ láti fún àwọn Aposteli ní agbára láti wàásù fún gbogbo ènìyàn (Ìṣe 2).

4. Ètò Ọlọ́run láti ìbẹ̀rẹ̀ ni pé gbogbo Orílẹ̀-èdè yóò gbà ìgbàlà:
Ọlọ́run ti sọ èyí tẹ́lẹ̀ ni
- Genesisi 12:3 pe' "Nípasẹ̀ Abrahamu ni gbogbo orílẹ̀-èdè yóò rí ìbùkún".
- Isaiah 49:6 wipe "Èmi yóò fi Ọ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn Keferi."
- Johanu 3:16 wípé "Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé to bẹ ẹ gẹ..."

Nítorí náà.
Israẹli ni ìgbàlà kọ́kọ́ dé, ṣùgbọ́n ní ikẹhin ìgbàlà de gbogbo ayé. {Hallelujah}.

Ní ṣókí:
- Jesu kò yí èrò Rẹ padà. Ó kan ń tẹ̀lé ètò Ọlọ́run ni. Ní ìbẹ̀rẹ̀, a rán àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sí Israẹli nítorí pé àwọn ni ènìyàn májẹ̀mú Ọlọrun. Sugbọn Lẹ́yìn ikú ati àjíǹde Jesu àti ìsọ̀kalẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́, a fi iṣẹ́ náà lé wọn lọ́wọ́ láti mú ìhìnrere lọ si gbogbo Ayé.
- Lẹ́yìn agbelebu àti àjíǹde, iṣẹ́ ìgbàlà ti pé. Nígbànáà ni a sí ilẹ̀kùn ihinrere silẹ fún gbogbo ènìyàn láìka Orílẹ̀-èdè tàbí ẹ̀yà sí.

Ní tòótọ́, ìwé Ìṣe Àwọn Aposteli fi hàn bí èyí ṣe ṣẹlẹ̀:
- Wọ́n bẹ̀rẹ̀ ní Jerusalemu.
- Lẹ́yìn náà sí Judea.
- Lẹ́yìn náà sí Samaria.
- Nígbẹ̀yìn, sí àwọn Keferi, nípasẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́ awọn Aposteli.

Nítorí náà, Matiu 10:5–6 jẹ́ àṣẹ fún àkókò kan, ṣùgbọ́n Matiu 28:19 àti Ìṣe 1:8 jẹ́ àṣẹ ti o kan gbogbo eniyan. Nitorina kò sí atakò nínú ipele ihinrere ti o kọja si ori Iran gbogbo eniyan.
------------------------------------------------
Bi ẹkọ yi ba ba igbe aye rẹ pade comment si abẹ post yi pe JESU NI OLUWA.

Edarapọ mọ WhatsApp group ẹkọ Bíbélì pẹlú WhatsApp link yi
👇👇👇
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw?s=cl&p=a&ilr=4

+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

OHUN TI O FA TI DAFIDI KO FI TETE DE IPO ỌBA LẸYÌN TI SAULU KU TAN."Iṣboṣeti ọmọ Saulu si jẹ ẹni ogoji ọdun nigbati o bẹ...
04/08/2026

OHUN TI O FA TI DAFIDI KO FI TETE DE IPO ỌBA LẸYÌN TI SAULU KU TAN.
"Iṣboṣeti ọmọ Saulu si jẹ ẹni ogoji ọdun nigbati o bẹrẹ si ijọba lori Israeli, o si jọba li ọdun meji. Ṣugbọn idile Juda ntọ̀ Dafidi lẹhin"
2Sam 2:10.

Lẹ́yìn ikú Saulu ní
1Samuel 31, Ọlọ́run ti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba. Ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli kò gba a gẹ́gẹ́ bí ọba lẹ́sẹ̀kẹsẹ.

Ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ báyìí:
1. Dafidi di ọba Juda nìkan: Ní 2Samuel 2:1–4, Dafidi lọ sí Hebron, àwọn ènìyàn ẹ̀yà Juda sì fi í jẹ ọba wọn. Ní àkókò yẹn, ó jọba lórí ẹ̀yà Juda nìkan, kì í ṣe lori gbogbo Israẹli.

2. Iṣboṣeti di ọba lórí ìyókù Israẹli.
Abineri, olórí ọmọ-ogun Saulu, mú Iṣboṣeti, ọmọ Saulu, lọ sí Mahanaimu, ó sì fi í jẹ ọba lórí àwọn ẹ̀yà yòókù ti Israẹli
(2Samueli 2:8–10).

Nípa bẹ́ẹ̀, orílẹ̀-èdè náà pín sí méjì:
- Dafidi jẹ Ọba lórí Juda.
- Iṣboṣeti jẹ Ọba lórí àwọn ẹ̀yà Israẹli tó kù.

3. Ogun abẹ́lé wà láàrín ilé Saulu àti ilé Dafidi. 2Samuel 3:1 sọ pé: "Ogun si pẹ́ láàrín ilé Saulu àti ilé Dafidi; Dafidi sì ń lágbára sí i, ilé Saulu sì ń rẹyin."

4. Dafidi di ọba gbogbo Israẹli.
Lẹ́yìn tí wọn pa Iṣboṣeti (2 Samueli 4), gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli wá sí Hebron, wọ́n sì fi Dafidi jẹ ọba gbogbo Israẹli
(2Samuel 5:1–5).

Nítorí náà, Dafidi ni Ọlọ́run yàn lẹ́yìn ikú Saulu, ṣùgbọ́n ní se ni ó kọ́kọ́ jẹ ọba lórí Juda nìkan fún ọdún méje àti oṣù mẹ́fà. Ní àkókò yẹn ni Iṣboṣeti, pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Abineri, jọba lórí àwọn ẹ̀yà Israẹli tó kù fún ọdún méjì. Lẹ́yìn ikú Iṣboṣeti ni Dafidi di Ọba gbogbo Israẹli. Eyi ni ìdí tí Bíbélì fi mẹ́nuba ìjọba àwọn méjèèjì láìsí àtakò.

ÁWỌN ẸKỌ MẸWA TI A RI KỌ NINU ÌSẸ̀LẸ̀ YI.
1. Àkókò Ọlọ́run yàtọ̀ sí ti ènìyàn:
Bí Ọlọ́run ṣe ti yan Dafidi kò túmọ̀ sí pé yóò jókòó lórí ìtẹ́ Ọba lẹ́sẹ̀kẹsẹ.
Oniw 3:1; Habk 2:3.

2. Ìlérí Ọlọ́run lè dojú kọ́ ìdènà, ṣùgbọ́n kò le bàjẹ́:
Ìjọba Iṣboṣeti kò lè fagilé ohun tí Ọlọ́run ti pinnu fún Dafidi.
Isa 14:27; Num 23:19.

3. Sùúrù jẹ́ ànímọ́ pàtàkì ninu ẹni tí Ọlọ́run yoo lo:
Dafidi kò gba ìjọba náà nípasẹ̀ ìwà ipá.
Psalm 27:14
Jakobu 5:7–8.

4. Má ṣe lo ọ̀nà àìtọ́ láti mú ìlérí Ọlọ́run ṣẹ:
Dafidi kò pa Iṣboṣeti tàbí fi agbára gba ìtẹ́ ọba lọwọ rẹ.
Romu 12:19.

5. Àwọn ènìyàn lè kọ ẹni tí Ọlọ́run ti yàn:
Ẹ̀yà mọkanla ninu mejila awọn ọmọ Israẹli ni wọn tẹ̀lé ilé Saulu dípò Dafidi.
John 1:11.

6. Àtìlẹ́yìn ènìyàn kò tó bí àtìlẹ́yìn Ọlọ́run:
Abineri gbìyànjú láti mú ilé Saulu dúró, sùgbọ́n Ọlọrun ni o ba awọn ètò rẹ na jẹ: Psalm 118:8–9.

7. Ọlọ́run máa ń kọ́ olórí nípasẹ̀ ìrírí:
Kí Dafidi tó di ọba gbogbo Israẹli, ó ti kọ́ ìdarí lórí Juda.
Luke 16:10.

8. Ìjà lè ṣáájú ìṣẹ́gun:
Ilé Dafidi àti ilé Saulu jagun fún ìgbà díẹ̀ kí àlàáfíà tó dé.
2Timothy 2:3
John 16:33.

9. Ohun tí a kọ lórí ìfẹ́ ènìyàn kò pé:
Ìjọba Iṣboṣeti dá lórí agbára Abineri, kì í ṣe nipa yíyan láti ọdọ Ọlọ́run, nítorí náà kò dúró. Psalm 127:1.

10. Ètò Ọlọ́run ṣẹ ní ìparí:
Lẹ́yìn gbogbo ìdènà, Dafidi di ọba gbogbo Israẹli gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti sọ.
Isaiah 46:10
Filipi 1:6.

NI IPARI.
Ìtàn Dafidi àti Iṣboṣeti kọ́ wa pé yíyan Ọlọ́run ko túmọ̀ sí pé ohun gbogbo máa rọrùn. Didúró de àkókò Ọlọ́run, sùúrù, ìgbọràn, àti ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa ni ń mú ẹni dé ibi tí Ọlọ́run ti pèsè fún un ni.
------------------------------------
Adio ẹkọ yi wa nilẹ fún gbogbo ọmọ Ọlọrun ti o ba fẹ, nitorina ẹdarapo mọ WhatsApp group ẹkọ Bibeli fun gbogbo ọmọ Ọlọrun ti o nifẹ si ojúlówó ẹkọ ọrọ Ọlọrun bi ti igbaani pẹlu Whatsapp link yi:

https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw?s=cl&p=a&ilr=4

04-08-2026.
+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

OHUN KAN NIPA ỌLỌRUN.Ohun kan nípa Ọlọ́run ni pé:- Ọlọrun ki i saba fi arahan ni ìbẹ̀ẹ̀rẹ̀ ogun, wàhálà ati ilakọja wa.-...
29/07/2026

OHUN KAN NIPA ỌLỌRUN.
Ohun kan nípa Ọlọ́run ni pé:
- Ọlọrun ki i saba fi arahan ni ìbẹ̀ẹ̀rẹ̀ ogun, wàhálà ati ilakọja wa.
- Nígbà miran ti ohun gbogbo ba le tan, ti o da bi ẹnipe ko si ojútùú mọ, ni ìgbà náà ni Olúwa sábà máa ń ṣiṣẹ́. Kì sábà wá ní àsìkò tí awa ro wípé yóò wa, ṣùgbọ́n ní àsìkò tí a ro wípé oti parí. Ọlọrun ma n se èyí gẹ́gẹ́ bí ète Rẹ̀, kí ògo isẹgun Wa ba le jẹ tirẹ nikan {2Kor 20:15}.
- Nígbà tí gbogbo ọ̀nà bá ti di, ti agbára ènìyàn bá ti pin, tí ọgbọ́n ayé sì ti sọ pé ohun gbogbo ti parí, nígbà naa ni Ọlọ́run máa ń fara hàn ní ọ̀nà ìyanu. Ọlọrun ń ṣe bẹ́ẹ̀ kí A lè mọ̀ pé kì í ṣe agbara tàbí ipa Wa ni a fi se bikose agbára Rẹ {Sakariah 4:6}.
- Nítorí náà, gbogbo ìgbà tí ohun gbogbo bá dà bí ẹni pé kò ṣeé ṣe mọ, ó yẹ kí ó jẹ́ ìránnilétí fún wa pé Ọlọ́run ṣì jẹ́ Ọlọ́run, kò sì sí ohun tí ó ṣòro jù fún Un lati se
{Jer 32:27}.
-----------------------------------------------------------------------
✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️
Efi comment yin s'ọwọ si abẹ ẹkọ yi fun ibeere, tabi ọrọ ìmọ riri.
-----------------------------------------------------------------------
Anfani wa fun yin lati darapọ̀ mọ WhatsApp group ile ise-iranse yi nibiti ẹ o ti ma gba awọn audio ẹkọ ti o wa lati ile ise-iranse yi ni ọfẹ.
Edarapọ pẹlu WhatsApp link 🔗 yi.
👇👇👇
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw
-----------------------------------------------------------------------
+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

ISE TI JESU RANSI IJỌ SMYRNA IFIHAN 2:8-11.Iṣẹ ti Jesu Kristi rán sí ìjọ Smyrna jẹ ọ̀kan lára àwọn lẹ́tà méje tí ó wà ní...
25/07/2026

ISE TI JESU RANSI IJỌ SMYRNA IFIHAN 2:8-11.
Iṣẹ ti Jesu Kristi rán sí ìjọ Smyrna jẹ ọ̀kan lára àwọn lẹ́tà méje tí ó wà nínú ìwé Ìfihàn. Ìjọ yìí jẹ́ ọ̀kan nínú ìjọ méjì ti o peregede pẹ̀lú ìjọ Filadelfíà awọn Ijọ meji ninu meje tí Jesu kò bá wí rárá, dípò bẹ́ẹ̀, ó fún wọn ní ọrọ ìṣírí nínú ìpọ́njú àti ilakọja wọn.

ÌLÚ SMYRNA.
Smyrna jẹ́ ìlú ọlọ́rọ̀ tí ó sì ṣe pàtàkì ní ilẹ̀ Asia ni akoko na. Ó jẹ́ ibi tí wọ́n ti ń sin ọba Romu àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òrìṣà. Èyí mú kí ìgbé ayé àwọn Kristẹni níbẹ̀ le gan-an, nítorí pé wọ́n kọ̀ láti jọsìn fún àwọn òrìṣà ilẹ na.

1. IDANIMỌ JESU KRISTI NI {ẸSẸ 8}.
Jesu bẹ̀rẹ̀ lẹ́tà náà nípa sísọ ẹni tí òun jẹ́: "Ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìkẹyìn, ẹni tí ó ti kú, tí ó sì tún yè.
"Ìdí tí Jesu fi lo orúkọ yìí nipe' Smyrna jẹ́ ìlú tí ó ti fẹ́rẹ̀ẹ́ parun rí ṣùgbọ́n tí ó tún padà dìde. Pẹ̀lú èyí, ọ̀pọ̀ àwọn Kristẹni ní Smiina ni wọ́n dojú kọ ikú nítorí ìgbàgbọ́ wọn. Jesu rán wọn létí pé òun ti borí ikú, nítorí náà, wọn kò gbọ́dọ̀ bẹ̀rù ikú mọ.

2. NI ẸSẸ IKẸSAN {ẸSẸ 9}JESU MỌ IPO TI ÌJỌ YI WA ATI ILAKỌJA WỌN.
Ni ẹsẹ kẹsán Jesu sọ pé òun mọ nǹkan mẹ́ta nípa Ijọ yi:
- Ìpọ́njú wọn: Wọ́n ń jìyà nítorí ìgbàgbọ́ wọn.
- Ìṣẹ́ wọn: Wọ́n jẹ́ tálákà nípa ti ara (nítorí wọ́n lè ti gba ohun-ìní wọn lọ́wọ́ wọn), ṣùgbọ́n Jesu sọ pé "olówó ni wọn" nípa ti ẹ̀mí.
- Sísọ ọ̀rọ̀-òdì àwọn ọ̀tá: Àwọn kan tí wọ́n pe ara wọn ní Júù ṣùgbọ́n tí wọ́n jẹ́ "sinagọgu ti Satani" ń sọ̀rọ̀-òdì sí wọn. Èyí tọ́ka sí àwọn tí wọ́n ń fìbínú fi ẹsun kan àwọn Kristẹni lọ́dọ̀ àwọn aláṣẹ Romu nigbana.

3. ỌRỌ IMULỌKANLE ATI IMỌRAN JESU FÚN IJỌ YI NI ẸSẸ KẸWA {ẸSẸ 10}.
Jesu kò ṣèlérí pé ìpọ́njú náà yóò kásẹ̀ nílẹ̀ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. Ó sọ fún wọn pé:
- Ẹ má bẹ̀rù: Jesu gb'awọn ni iyànjú lati máṣe bẹrù ìyá ti wọn n bọ wa jìyà rẹ. Jesu sọ fún wọn pe Esu yóò ju nínú wọn sínú túbú láti dán wọn wò.
- Ọjọ́ mẹ́wàá: Jesu wípé ìpọ́njú náà yóò wà fún "ọjọ́ mẹ́wàá". Èyí túmọ̀ sí pé ìpọ́njú náà yóò ní àkókò tí yóò parí, kò ní pẹ́ títí láé.
- Jẹ́ olódodo títí de ikú: Èyí ni àṣẹ àti ìmọràn tí Jesu fún wọn.

4. ÌLÉRÍ TI JESU FÚN ÌJỌ YI NI ẸSẸ KẸWA SI IKỌKÀNLÁ
{ẸSẸ 10-11}.
Ileri ohun nla meji ni Jesu se fún Ìjọ yi bi o ba le foriti t**i de òpin.
- Adé Ìyè: Jesu se ileri ade iye fún Ìjọ yi bi o ba le se olootọ de oju iku.
- Ìṣẹ́gun lórí Ikú Kejì: Ẹni tí ó bá ṣẹgun kò ní f'arapa nínú "ikú kejì" (iyẹ ìyapa títí láé kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run).

NI IPARI.
Ìsẹ́ tí Jesu ransi ìjọ Smyrna kọ́ wa pé:
- Ọlọ́run mọ gbogbo ìṣòro wa, kódà nínú ìṣẹ́, ìpọ́njú ati ilakọja wa.
- Ìpọ́njú kì í ṣe àmì pé Ọlọ́run kọ̀ wa sílẹ̀.
- Ako gbọdọ bẹ̀rù ìnúnibíni tàbí ìjìyà nítorí Kristi.
- Ẹnití ó bá ṣẹ́gun yóò gba adé ìyè.
- Ìdúróṣinṣin títí de ikú ní èrè tí ó tóbi jùlọ, tí í ṣe ìyè títí láé.
-----------------------------------------------------------------------
✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️
Efi comment yin s'ọwọ si abẹ ẹkọ yi fun ibeere, tabi ọrọ ìmọ riri.
-----------------------------------------------------------------------
Anfani wa fun yin lati darapọ̀ mọ WhatsApp group ile ise-iranse yi nibiti ẹ o ti ma gba awọn audio ẹkọ ti o wa lati ile ise-iranse yi ni ọfẹ.
Edarapọ pẹlu WhatsApp link 🔗 yi.
👇👇👇
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw
-----------------------------------------------------------------------
+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

BI A SE LE KA BIBELI NI ỌNA TI A LE GBA LÓYE RẸ̀. Ohun ti o dara gbaa ni bi ènìyàn ba dantọ lati mọ ohun ti Ọlọrun n sọ ...
22/07/2026

BI A SE LE KA BIBELI NI ỌNA TI A LE GBA LÓYE RẸ̀.

Ohun ti o dara gbaa ni bi ènìyàn ba dantọ lati mọ ohun ti Ọlọrun n sọ láti inú ọrọ Rẹ.
Ọ̀na ti Stefanu fi gbe iwasu ikẹhin rẹ jáde jẹ èyí ti o kún fún iná agbara ọrọ Ọlọrun, èyí ni o si fi Stefanu hàn gẹgẹ bi ẹnití o dantọ ninu ìmọ Bíbélì àti ẹnití o ye ohun ti o wa ninu Bibeli ye.
Njẹ iwọ na fẹ de iru ipele ẹmi bayi bi?
Ise A A 7:1-60 {54-56}.
Ẹnití ko bá mọ ọrọ Ọlọrun dàbí ẹnití o sọ wúrà olowo iyebiye nu.

NITORINA O NILO LATI MỌ BI O SE LE KA BIBELI NI Ọ̀NÀ TÍ YOO FI YE Ọ.
Awọn ọna ti mo fẹ mẹnu ba yi, yoo rán ọ lọwọ dáadáa láti le jẹ ki Bibeli ye ọ ki o si le gba ìmísí nípa rẹ, nigbati o ba n ka Bibeli:

1. Setan lati wa ìmọ nipa rẹ (Bíbélì):
Ẹnití o fẹ ka Bibeli ni ọna ti yoo fi mọ ìtumọ rẹ gbọdọ le san owo idiyelé rẹ, ni awọn ọna wọnyi:
- Iru ẹnibẹ gbọdọ le se tan lati na owo si rira awọn orisirisi Bíbélì ati awọn iwe ìmọ nipa alaye Bíbélì.
- Iru ẹnibẹ gbọdọ le se tan lati ra ìmọ̀ ni ọdọ àwọn ti o ni imọ ijinlẹ nínú Bíbélì, nitori akoko imusẹ àsọtẹlẹ nipa iyan ọrọ Ọlọrun ni awa yi, nitorina ọmọ Ọlọrun ti yoo ba ni ojúlówó ìmọ̀ ọrọ Bíbélì ni akoko ti a wa yi gbọdọ se tan lati fun ni ohun gbogbo ti o ba gba.
📚"Kiyesi i, ọjọ na de, li Oluwa Ọlọrun wi, emi o rán iyàn wá si ilẹ na, kì iṣe iyàn onjẹ, tabi ongbẹ fun omi, ṣugbọn iyàn gbigbọ́ ọ̀rọ Oluwa: Amosi 8:11.
📚"Ijọba ọrun si dabi iṣura ti a fi pamọ́ sinu oko, ti ọkunrin kan ri, ti o pa a mọ́; nitori ayọ̀ rẹ̀, o lọ, o si ta gbogbo ohun ti o ni, o si rà oko na" Mat 13:44.
📚"Ati pẹlu, ijọba ọrun si dabi ọkunrin oniṣowo kan, ti nwá perli ti o dara:
Nigbati o ri perli olowo iyebiye kan, o lọ, o si tà gbogbo nkan ti o ni, o si rà a Mat 13:45-46.
📚"Ofin ẹnu rẹ dara fun mi jù ẹgbẹgbẹrun wura ati fadaka lọ" Psalm 119:72.

2. Beere fún imisi Emimọ nínú àdúrà:
Ki o to bẹrẹ kika Bibeli gbàdúrà kí Ọlọ́run fún ọ ní ọgbọ́n àti ìmọ̀ láti lóye awọn ẹsẹ ti o fẹ ka.
"Là mi ni oju, ki emi ki o le ma wò ohun iyanu wọnni lati inu ofin rẹ.
Psalm 119:18.

3. Ya akoko ijiroro rẹ sọtọ:
Ohun ti o dara julọ ti a ba fẹ ka Bibeli ni ọna ti a o fi gba' ìtumọ rẹ ni ọwọ Emi-mimo ni ki a ya akoko kika Bibeli sọtọ láàrin "àwọn akoko aniyan wa" paapa julọ fún awa ti òye nipa gbigba ìmísí ninu ọrọ Ọlọrun ko ba i ti ma ye daada.
📚"Isaaki si jade lọ ṣe àṣaro li oko li aṣalẹ ----" Gen 24:63.

4. Ka ní ìtòlẹ́sẹẹsẹ:
Bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ẹsẹ kan kí o si ri wipe o gba ìmísí itumọ lórí ẹsẹ na ki o to tun lọ si ẹsẹ miran Job 2:4.

5. Mọ awọn n kan yi:
Fún ẹnití o ye bíbélì ko i ti ma ye daada, fún ẹnití o sẹsẹ fẹ bẹrẹ lati ma ka bibeli, ma ti kánjú lọ ma ka awọn iwe wọnyi:
- Eksodu
- Numeri
- Deuteronomi
- Danieli
- Ìfihàn
- Kronika
- Ẹkun Jeremiah
- Matiu 1:1-17 ati awọn iwe miran. Nítorí awọn ọrọ ijinlẹ pọ ninu awọn iwe yi.
Fún ẹnití o ye awọn ìtumọ ẹsẹ ọrọ ko i ti ma ye daadaa. Odara púpọ ki ẹnina bẹrẹ ijiroro Bibeli kika rẹ ninu awọn iwe Bibeli wọn yi:
- Jenesisi
- Awọn ori ti o saaju ninu iwe Joshua.
- Samueli
- Esteri
- Iwe Johanu✓
ati awọn iwe miran. Awọn iwe wọnyi dara fun awọn asẹsẹ bẹrẹ tabi awọn ti ọrọ inu Bibeli ko i ti ma ye daadaa nitori wọn jẹ awọn iwe:
- Itan.
- Ìsẹlẹ.
- Ìtumọ awọn ọrọ inu wọn lọ ni geerere.

6. Wo àyíká ẹsẹ Bibeli ti o fẹ ka náà (Context):
Má ṣe yọ ẹsẹ kan kúrò ní àyíká rẹ. Ka ẹsẹ ti o ṣáájú àti ẹsẹ ti o tẹ̀lé e.

7. Fi Bíbélì sàlàyé Bíbélì: Fi àwọn ẹsẹ míì tó sọ nípa kókó kan wé ara wọn
2Tim 3:16-17.

8. Mọ irú ìwé tí o ń ka:
Diẹ̀ jẹ́ ìtàn, diẹ̀ jẹ́ orin, owe, asọtẹ́lẹ̀, lẹ́tà, tàbí ìran. Ìyẹn máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti mọ̀ ìtumọ wọn dáadáa.

9. Se àkọsílẹ̀:
- Kọ ohun tí o kọ́ silẹ.
- Kọ àwọn ohun ti ko ye ọ silẹ, ki o si beere lọwọ àwọn òbí tabi awọn alagbatọ rẹ ninu Oluwa.

10. Lo àwọn ìtọ́kasí Bíbélì: Se awárí àwọn ẹsẹ tó jọra (cross references) láti ní òye tó jinlẹ̀ síi. Fun apẹrẹ
Ni atetekose Jenesisi 1:1 yatọ si' ni atetekose
Johanu 1:1.

11. Lo Bíbélì ti ìtumọ ede rẹ rọ run:
Bí o bá lè se é, fi àwọn ìtumọ̀ Bíbélì méjì tàbí mẹ́ta wé ara wọn láti lóye àwọn ọ̀rọ̀ tó nira nítorí ani ọpọ awọn orisirisi ìtumọ (version) Bíbélì bi:
- KJV (King James Version)
- NKJV (New King James Version)
- NIV (New International Version)
- ESV (English Standard Version)
- NASB (New American Standard Bible)
- CSB (Christian Standard Bible)
- NLT (New Living Translation)
- GNT/GNB (Good News Translation/Bible)
- RSV (Revised Standard Version)
- NRSV (New Revised Standard Version)
- AMP (Amplified Bible)
- The Message (MSG)
- Good news.

12. Gbé ohun tí o kà sí ìṣe: Ìmọ̀ Bíbélì máa jinlẹ̀ síi nígbà tí a bá ń gbé aye wa gẹ́gẹ́ bí ìlànà àwọn ohun ti a ka. "Ṣugbọn ki ẹ jẹ oluṣe ọ̀rọ na, ki o má si ṣe olugbọ́ nikan, ki ẹ mã tàn ara nyin jẹ" Jakọbu 1:22.

13. Máa ka Bíbélì ní gbogbo ọjọ́: Ìfaradà àti ìtẹ̀síwájú ni ń mú ìmọ̀ jinlẹ̀.
"Iwé ofin yi kò gbọdọ kuro li ẹnu rẹ, ṣugbọn iwọ o ma ṣe àṣaro ninu rẹ̀ li ọsán ati li oru, ki iwọ ki o le kiyesi ati ṣe gẹgẹ bi gbogbo eyiti a kọ sinu rẹ̀: nitori nigbana ni iwọ o ṣe ọ̀na rẹ ni rere, nigbana ni yio si dara fun ọ"
Joṣua 1:8.

14. Béèrè lọwọ ara rẹ nígbà gbogbo ti o ba n ka Bibeli wipe:
- Ta ni ó kọ ọ iwe yi?
- Ta ni a kọ ọ sí?
- Kí ni ìdí tí a fi kọ ọ?
- Kí ni ẹsẹ náà túmọ̀ sí?
- Báwo ni mo ṣe lè fi sí ìṣe lónìí?
-----------------------------------------------------------------------
✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️
Efi comment yin s'ọwọ si abẹ ẹkọ yi fun ibeere, tabi ọrọ ìmọ riri.
-----------------------------------------------------------------------
Anfani wa fun yin lati darapọ̀ mọ WhatsApp group ile ise-iranse yi nibiti ẹ o ti ma gba awọn audio ẹkọ ti o wa lati ile ise-iranse yi ni ọfẹ.
Edarapọ pẹlu WhatsApp link 🔗 yi.
👇👇👇
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw
-----------------------------------------------------------------------
+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

IGI GOFERI ATI ẸKỌ TI O KỌ WA NIPA TẸMI.- Igi Gòfẹ́rí jẹ́ igi tó lágbára.- Ojẹ igi ti o ga ti o si tọọ.- Ojẹ igi tí kò r...
21/07/2026

IGI GOFERI ATI ẸKỌ TI O KỌ WA NIPA TẸMI.

- Igi Gòfẹ́rí jẹ́ igi tó lágbára.
- Ojẹ igi ti o ga ti o si tọọ.
- Ojẹ igi tí kò rọrùn láti bàjẹ́.
- O ni agbara lati gbe ẹrù n la si ori rẹ.
- O jẹ igi ti o mi ki i tete ri aye lati baajẹ.
- O rorun lati ri ni akoko na.
Ni akoko Bibeli wọn máa ń lò ó fún ilé kikọ. Ati sise ọkọ̀ ojú omi, àti àwọn ohun isẹ ọna míràn.
Ninu iwe Genesis 6:14 ni kan soso ni a ti gburo orúkọ igi yi. Kò sí ibòmíràn nínú Bíbélì, yálà nínú Májẹ̀mú Láéláé tàbí Májẹ̀mú Tuntun, tí a tún ti dárúko igi yìí mọ. Èyí ni ó jẹ́ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn máa ṣe ìwádìí lórí irú igi tí ó jẹ́ gan-an.

IDITI O FI JẸ PE IGI YI NI ỌLỌRUN YAN.
Ìdí pàtàkì tí Ọlọ́run fi yan igi yìí ni pé' o jẹ́ igi tó yẹ fún iṣẹ́ náà. Ọkọ̀ Nóà gbọ́dọ̀ lágbára, ó gbọ́dọ̀ lè farada ìkún omi tó lágbára, ki awọn ti o ba wọ inú rẹ le ni aabo ti o pe ye.

Àkíyèsí.
Ìdí pàtàkì tí Ọlọ́run fi sọ irú igi tí Nóà yóò lò fi hàn pé Ọlọ́run mọ ohun gbogbo, ó sì fẹ́ kí Nóà tẹ̀lé àwọn ìlànà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ. Èyí fi hàn pé Ọlọ́run ni ó mọ ohun tó dára jù lọ fún ààbò àti ìgbàlà àwọn ènìyàn rẹ̀.

ẸKỌ TI EYI KỌWA:
Lílo igi Goferi láti kan ọkọ̀ Nóà jẹ aṣẹ láti ọdọ Ọlọrun èyí ti o ni ẹkọ ijinlẹ̀ tẹmi tí a lè rí kọ́.
Àwọn ẹ̀kọ́ náà nìyí:
1. Ìgbọ́ràn ní kíkún (Complete Obedience):
Ọlọ́run kò sọ fún Nóà pé kó lo "igi èyíkéyí," Ó fún un ní ìtọ́ni pàtó láti lo igi Goferi. Èyí kọ́ wa pé nínú ìrìn àjò wa pẹ̀lú Ọlọ́run, ìgbọ́ràn ní kíkún ṣe pàtàkì. Nóà kò fi ọgbọ́n orí rẹ̀ rọ́pò ọgbọ́n Ọlọ́run. Bí a bá fẹ́ rí ìgbàlà àti ìbùkún Ọlọ́run, a gbọ́dọ̀ tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ paapajulọ awa ti a jẹ òsìsẹ́ ninu ijọ ati awa iransẹ Ọlọrun.

2. Ààbò àti Ètùtù (Protection and Atonement):
Ẹ̀kọ́ tẹ̀mí tó jinlẹ̀ jù lọ wà nínú ọ̀rọ̀ náà "Goferi" àti "Ọ̀dà" (pitch) tí wọ́n fi kùn ún. Gen 6:14.
- Nínú èdè Hébérù, ọ̀rọ̀ tí wọ́n lò fún "ọ̀dà" ni kopher, ọ̀rọ̀ ìṣe rẹ̀ sì ni kaphar.
- Ọ̀rọ̀ yìí náà (kaphar) ni Bíbélì lò fún "Ètùtù" (Atonement).
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dà náà ṣe bo igi Goferi mọ́lẹ̀ láti dènà omi kí ó má bàa wọ inú ọkọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀jẹ̀ Jésù Krístì ṣe jẹ́ ètùtù fún wa, tó bò wá mọ́lẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìdájọ́ ẹ̀ṣẹ̀. Èyí jẹ́ àpẹẹrẹ bí Ọlọ́run ṣe ń pèsè ọ̀nà abayọ fún wa nínú ìdájọ́.

3. Agbára láti kojú ìdánwò (Durability and Resilience):
Wọ́n mọ igi Goferi (tí ọ̀pọ̀ gbà pé ó jẹ́ Cypress) sí igi tí kì í tètè jẹrà tàbí kí kòkòrò jẹ ẹ́. Nípa tẹ̀mí, èyí kọ́ wa pé ìpìlẹ̀ ìgbésí ayé wa gbọ́dọ̀ jẹ́ ohun tó lágbára. Láti la "ìkún omi" ayé yìí já (àwọn ìṣòro, àdánwò, àti ẹ̀tàn), a nílò láti kọ ìgbésí ayé wa lórí nǹkan tẹ̀mí tó lágbára, èyí tí í ṣe Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí kì í bajẹ tàbí jẹrà.

4. Ìpèsè Ọlọ́run (God’s Provision):
Ọlọ́run mọ irú ìjì tó máa jà, ó sì mọ irú igi tó lè kojú rẹ̀. Èyí kọ́ wa pé Ọlọ́run mọ ohun tí a nílò gangan láti la ipò tí a bá ara wa. Kò jẹ́ kí Nóà lo igi tí kò ní lè gbé e ró. Nínú ayé ti a wa náà, Ọlọ́run ti pèsè "igi Kóferì" tẹ̀mí (ìyẹn ni agbára Ẹ̀mí Mímọ́ àti Ọ̀rọ̀ Rẹ̀) fún wa láti fi borí ìṣòro èyíkéyí.

5. Ìfaradà àti Iṣẹ́ Ìgbàgbọ́:
Kíkán ọkọ̀ pẹ̀lú igi Goferi gba àkókò àti ìsapá. Nóà lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún láti fi igi náà kan ọkọ̀. Èyí kọ́ wa pé ìgbàlà kì í ṣe irin ajo ọjọ kan. Ó gba ìfaradà, sùúrù, àti ṣíṣe iṣẹ́ ìgbàgbọ́ ní ojoojúmọ́ títí tí ìgbàlà náà yóò fi pé. Pipe ìgbàlà wa di igbati a ba gbawala sinu ijọba ayérayé ti Jesu.
Nítorí náà, igi Kófẹ́rì jẹ́ àmì ìgbọ́ràn, ètùtù, àti agbára tẹ̀mí tí Ọlọ́run fún wa láti fi la awọn akoko wahala ayé yìí já.
-----------------------------------------------------------------------
✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️✍️
Efi comment yin s'ọwọ si abẹ ẹkọ yi fun ibeere, tabi ọrọ ìmọ riri.
-----------------------------------------------------------------------
Anfani wa fun yin lati darapọ̀ mọ WhatsApp group ile ise-iranse yi nibiti ẹ o ti ma gba awọn audio ẹkọ ti o wa lati ile ise-iranse yi ni ọfẹ.
Edarapọ pẹlu WhatsApp link 🔗 yi.
👇👇👇
https://chat.whatsapp.com/F7TSdwr1fKh1wKO8HXjIKw
-----------------------------------------------------------------------
+2348124247703
Olasunkanmi
Alabi Jesumbo.

Address

Ibadan

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when Bttop Media "Epada si oju ona igbaani" posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Contact The Place Of Worship

Send a message to Bttop Media "Epada si oju ona igbaani":

Shortcuts

Share