CAC Living Water Daily Devotional

CAC Living Water Daily Devotional THIS PAGE PROVIDES YOU WITH CHRIST APOSTOLIC CHURCH DAILY DEVOTIONAL (LIVING WATER-OMI-IYE) AND SUNDAY SCHOOL LESSONS.

26/08/2026

ÌJỌ ÀPỌ́SÍTÉLÌ KRISTI
Naijiria àti Oke Okun

OMI IYE NAA, (January- December, 2026)

Ọjọru (Wednesday), August 26, 2026.

ÀKÒRÍ:
TITẸSIWAJU SII PẸLU JESU (1)

AKỌSORI:

Ṣugbọn nigbati Jesu gbọ́, o da a li ohùn, wipe, Má bẹ̀ru: gbagbọ́ nikan ṣa, a o si mu u larada (Luku 8:50).

KA:
Luku 8:49-56

[49]. Bi o si ti nsọ̀rọ li ẹnu, ẹnikan ti ile olori sinagogu wá, o wi fun u pe, Ọmọbinrin rẹ kú; má yọ olukọni lẹnu mọ.

[50]. Ṣugbọn nigbati Jesu gbọ́, o da a li ohùn, wipe, Má bẹ̀ru: gbagbọ́ nikan ṣa, a o si mu u larada.

[51]. Nigbati Jesu si wọ̀ ile, kò jẹ ki ẹnikẹni wọle, bikoṣe Peteru, ati Jakọbu, ati Johanu, ati baba on iya ọmọbinrin na.

[52]. Gbogbo nwọn si sọkun, nwọn pohùnrere ẹkún rẹ̀: o si wi fun wọn pe, Ẹ má sọkun mọ́; kò kú, sisùn li o sùn.

[53]. Nwọn si fi i ṣẹ̀fẹ, nwọn sa mọ̀ pe o kú.

[54]. Nigbati o si sé gbogbo wọn mọ́ ode, o mu u li ọwọ́, o si wipe, Ọmọbinrin, dide.

[55]. Ẹmí rẹ̀ si pada bọ̀, o si dide lọgan: o ni ki nwọn ki o fun u li onjẹ.

[56]. Ẹnu si yà awọn õbi rẹ̀: ṣugbọn o kilọ fun wọn pe, ki nwọn ki o máṣe wi fun ẹnikan li ohun ti a ṣe.

ITUPALẸ:

Jesu sábà maa n ba awọn ọmọ ẹyin Rẹ sọrọ, ti o duro lori ipele igbagbọ wọn ati bi wọn ṣe dagba tojuubọ ninu ẹmi si, gẹgẹ bi a ṣe ri ninu awọn apẹẹrẹ nibi ti yóò ti sọ fun awọn ọmọ ẹyin mẹsàn -an lati duro lẹyin nigba ti Oun yóò si tẹsiwaju pẹlu awọn mẹta. Ninu ibi kika ti òni, Jairu pe Jesu lati wá wo ọmọde binrin rẹ ti o n kú lọ sản, Jesu gbà, Ó si bẹrẹ irinajo lọ si ilé Jairu. Ṣugbọn ọ̀pọ̀ èrò yi I ká, eyi ti o mu ki irin Rẹ ki o falẹ. Nigba ti wọn de ilé Jairu, Jesu gba awọn perete láàyè lati tẹsiwaju pẹlu Rẹ. Awọn mẹsan-an ti o kù n kọ?

Ninu irin ajo Kristẹni wa, ọpọlọpọ ni o n tẹlé Jesu, ṣugbọn awọn kan kò ni ireti kan pató. Wọn kò tii ni iriri iṣẹ ami Ọlọrun ti kò ni abùlá ojukooju: wọn kan n gbọ nipa wọn ni. Awọn ẹlomiran dà bi awọn èro iwòran ni ilé Jairù, ti wọn n ṣe iyemeji nipa iṣẹ iyanu ti wọn si n yára lati yọ sùti ètè sí ijakulẹ. Ohun ibanujẹ ni pe ọpọ awọn onigbagbọ a maá dúró láảrin awọn èro, ti wọn si n padanu awọn ijinlẹ ibukún igbagbọ.

Iriri wa pẹlu Ọlọrun dá lóri Igbagbọ wa ati bi a ṣe dàgba tojuubọ si. Lati lè ri awọn iṣẹ àmi ati iyanu, a gbọdọ máá dàgbà ni ojoojumọ nipa bíbá Kristi rin timọtimọ. Awọn iṣẹ Rẹ tẹsiwaju ati pé titẹsiwaju pẹlu Rẹ a máa mú awọn iriri agbara Rẹ wá lọna tí o yatọ. Njẹ o n fojusọna fún iṣẹ àmi Ọlọrun bi? Gbé igbésẹ̀ igbagbọ ki o si tẹsiwaju pẹlu Jesu

Awọn koko Adura

1. Olúwa, fi kún igbagbọ mi ki O si ràn mi lọwọ lati tẹsiwaju pẹlu Rẹ ni ojoojumọ.

2. Baba, mu gbogbo idiwọ ti o n fa mi sẹyin ninu irin mi pẹlu Rẹ kuro.

3. Gbàdúrà fún àfikún agbara ati iwàláàyè Ọlọrun ní CAC Ẹkun Gbooro Anosike, ninu aye baba wa, Alabojuto Ẹkun naa, awọn oloye miiran ati awọn ọmọ ijọ ni oniruuru ipele, ni orukọ Jesu.

Orin Ti A Dabaa Fun Oni:
C.A.CGHB: 627

OKOOLELẸGBẸTA O LE MEJE

8 8 8 D

Nitoriti a fi ipinlẹ rẹ sọlẹ lori apata.
Mat. 7:25

1. Igbagbo mi duro l'ori,
Eje at' ododo Jesu,
Nko je gbekele ohun kan,
Leyin oruko nla Jesu.

Mo duro le Kristi Apata,
Ile miran, iyanrin ni.

2. B'ire-ije mi tile gun,
Or'-ofe Re ko yi pada;
B'o ti wu ki iji na le to
Idakoro mi ko niye.

3. Majemu, ati eje Re
L'em'o ro mo, bi 'kun mi de;
'Gbati ko s'atileyin mo
On je ireti nla fun mi.

4. 'Gbat'ipe 'keyin ba si dun,
A! mba le wa ninu Jesu;
Ki nwo ododo Re nikan
Ki nduro niwaju ite.

Amin.

Afikun Ibi kika Fun Oni:
Jeremáyà 15 - 17

26/08/2026

CHRIST APOSTOLIC CHURCH
[Nigeria and Overseas]

THE LIVING WATER [January-December, 2026]

DAILY DEVOTIONAL GUIDE

DATE:
Wednesday, 26th August, 2026

TOPIC:
GOING FURTHER WITH JESUS (I)

MEMORISE

But when Jesus heard it, He answered him, saying, Do not be afraid: only believe, and she will be made well' (Luke 8:50).

READ:
Luke 8:49-56

[49]. While He was still speaking, someone came from the ruler of the synagogue’s house, saying to him, “Your daughter is dead. Do not trouble the Teacher.”

[50]. But when Jesus heard it, He answered him, saying, “Do not be afraid; only believe, and she will be made well.”

[51]. When He came into the house, He permitted no one to go in except Peter, James, and John, and the father and mother of the girl.

[52]. Now all wept and mourned for her; but He said, “Do not weep; she is not dead, but sleeping.”

[53]. And they ridiculed Him, knowing that she was dead.

[54]. But He put them all outside, took her by the hand and called, saying, “Little girl, arise.”

[55]. Then her spirit returned, and she arose immediately. And He commanded that she be given something to eat.

[56]. And her parents were astonished, but He charged them to tell no one what had happened.

EXPOSITION

Jesus often related to His disciples based on their level of faith and spiritual maturity, as seen in various instances where He would ask nine disciples to stay behind while He went further with the other three. In today passage, Jairus invited Jesus to heal his dying daughter. Jesus agreed and began the journey to Jairus' house. However, a large crowd surrounded Him, slowing His movement. When they reached Jairus' house, Jesus allowed only few persons to go further with Him. What about the other nine disciples?

In our Christian journey, many follow Jesus, but some have no real expectations. They have not experienced God's wonders firsthand, they only hear about them. Others are like the spectators in Jairus' house, doubting miracles and quick to mock failures. Sadly, some believers stay behind with the crowd, missing deeper blessings of faith.

What we experience with God depends on our faith and maturity. To see His miracles and wonders, we must grow daily by walking closer with Christ. His works are progressive and going further with Him brings greater experiences of His power. Are you longing for God's miracles? Take steps of faith and go further with Jesus.

PRAYER POINTS

1. Lord, increase my faith and help me to go further with You daily.

2. Father, remove every distraction that holds me back in my walk with You.

3. Pray for more of God's power and presence in CAC Anosike Region, in the life of our father, the Regional Superintendent, other officers and members at various levels, in Jesus' name.

SUGGESTED HYMN FOR TODAY:
CACGHB: 627

8 8 8 D

1. My hope is built on nothing less
Than Jesus' blood and righteousness;
No merit of my own I claim,
But wholly lean on Jesus' name

Chorus:
On Christ, the solid rock, I stand;
All other ground is sinking sand.

2. When long appears my toilsome race,
I rest on His unchanging grace;
In every high and stormy gale,
My anchor holds within the veil

3. His oath, His covenant, and blood,
Support me in the whelming flood;
When every earthly prop gives way,
He then is all my hope and stay.

4. When the last trumpet's voice shall sound,
Oh may I then in Him be found.
Robbed in His righteousness alone,
Faultness to stand before the throne.

Amen.

EXTRA READING FOR TODAY:
Jeremiah 15-17

AUTHOR
CAC, Christian Education Department.

Stay blessed and fruitful for the glory of God.

25/08/2026

ÌJỌ ÀPỌ́SÍTÉLÌ KRISTI
Naijiria àti Oke Okun

OMI IYE NAA, (January- December, 2026)

Ọjọ Iṣẹgun (Tuesday),
August 25, 2026.

ÀKÒRÍ:
SÍSỌNÙ SÍNÚ IJỌ: Ọ̀RUN N YỌ

AKỌSORI:

Mo wi fun nyin, gẹgẹ bẹ̃li ayọ̀ yio wà li ọrun lori ẹlẹṣẹ kan ti o ronupiwada, jù lori olõtọ mọkandilọgọrun lọ, ti kò ṣe aini ironupiwada (Lúkù 15:7).

KA:
Luku 15:7

[7]. Mo wi fun nyin, gẹgẹ bẹ̃li ayọ̀ yio wà li ọrun lori ẹlẹṣẹ kan ti o ronupiwada, jù lori olõtọ mọkandilọgọrun lọ, ti kò ṣe aini ironupiwada.

ITUPALẸ:

Nigba ti ẹnikan ti ó sọnu bá yípadà sí Ọlọrun, ọrun a maa ṣe ajọyọ pẹlu ayọ nlá, Jesu ṣalaye èyi ninu awọn òwe Rẹ nipa fàdákà ti o sọnu ati agùntan ti o sọnu. Gbogbo eniyan ni o ṣe pataki si Ọlọrun, O si n fẹ ki gbogbo eniyan di ẹni igbala. Ni Luku 15 :7, Jesu sọ fún wa pé ayọ̀ pupọ wà ní ọrun lóri ẹlẹṣẹ kan ti o ronúpiwàdà ju lori awọn oloótọ́ ti kò nílò
ironúpiwàda

O jẹ ohun ibanujẹ pe ọpọ enyan ninu Ijọ și sọnu sibẹ gẹgẹ bi a ti kiyesi ninu awọn ẹkọ wa atẹyinwa, wọn a maa wá fún isin, wọn a maa Kọrin ki wọn si darapọ mọ awọn ètò gbogbo, ṣugbọn wọn kò ní ibaṣepọ tootọ́ pẹlu Ọlọrun. O jẹ ojuṣe wa lati ràn wọn lọwọ lati sàwárí igbàlà.

Ninu itàn fàdákà tí ó sọnù, obinrin náà tan fitilà o si wá a gidigidi t**i ti ó fi ri, èyi n kọ wa ki a tẹra mọ riran awọn ti kò ti i ní igbàlà lọwọ. Afojusun ṣiṣe bẹẹ kií ṣe pé ki ara awọn eniyan lè balẹ ninu ljọ nikan ṣugbọn ki a mú wọn wọ inu iyè ainipẹkun ninu Jesu Kristi nipasẹ awọn iwàásù tabi ẹkọ ọrọ Rẹ ti o ye kooro.

Mú iṣẹ pataki yii ni ọkunkúndùn. Ọ̀run n duro/reti lati yọ lori gbogbo ẹlẹṣẹ ti o bá yípadà sí Ọlọrun ni àyíká rẹ, gbadura fún awọn ti o yi ọ ká, ṣe ajọpin Ihinrere pẹlu ifẹ ki o si tọ́ wọn lọ si ọdọ Kristi. Akitiyan ti o bá sa yóò mú awọn eniyan wá sinu igbala yóò si fi ayọ nla kún ọrun.

Awọn koko Adura

1. Oluwa, ràn mi lọwọ lati ni ifaraji si igbala awọn ẹlomiran.

2. Baba, jẹ ki awọn iṣẹ mi ninu ikede ihinrere mú ki ayọ wà ni ọrun.

3. Gbadura fún CAC JABU, awọn olori, awọn oṣiṣẹ ati awọn akẹkọọ gẹgẹ bi Ẹmi Ọlọrun bá ṣe dari rẹ.

Orin Ti A Dabaa Fun Oni: C.A.CGHB: 432

OJILENIRINWO O DIN MẸJỌ

6 6 6 6 8 8

O ti ran mi lati kede idasilẹ fun awọn igbekun.
Isa. 61:1

1. E fun 'pe na kikan,
Ipe ihinrere;
K'o dun jake jado
L'eti gbogbo eda:

Odun idasile ti de
Pada elese, e pada.

2. Jesu Alufa wa
Ti s'etu lasepe:
Alare, e simi,
Asofo, tujuka.

3. Fun'pe t'Od'agutan
Ta ti pa setutu;
Je ki agbaye mo
Agbara eje Re

4. Eyin eru ese;
E so ra yin d'omo;
Lowo Kristi Jesu,
E gb'ominira yin.

5. Gbo 'pe ihinrere,
Ihin ore-ofe;
Agba yin low' aye,
E wa 'waju Jesu.

Amin.

Afikun Ibi kika Fun Oni:
Jeremáyà 12 - 14.

25/08/2026

CHRIST APOSTOLIC CHURCH
[Nigeria and Overseas

THE LIVING WATER [January-December, 2026]

DAILY DEVOTIONAL GUIDE

DATE:
Tuesday, 25th August, 2026

TOPIC:
LOST IN THE CHURCH: HEAVEN REJOICES

MEMORISE

I say to you that likewise there will be more joy in heaven over one sinner who repents than over ninety-nine just persons who need no repentance (Luke 15:7).

READ:
Luke 15:7

[7]. I say to you that likewise there will be more joy in heaven over one sinner who repents than over ninety-nine just persons who need no repentance.

EXPOSITION

When someone who is lost turns to God, heaven celebrates with great joy. Jesus explained this in His parables about the lost coin and the lost sheep. Every person is precious to God and He wants everyone to be saved. In Luke 15:7, Jesus tells us that there is more joy in heaven over one sinner who repents than over many righteous people who do not need repentance.

Sadly, some people in the Church are still lost. Like we observed in our previous doses, they attend services, sing and join activities, but they lack true relationship with God. It is our responsibility to help them find salvation.

In the story of the lost coin, the woman lit a lamp and searched carefully until she found it. This teaches us to put effort into helping the unsaved. The goal is not just to make people feel comfortable in the Church but lead them to eternal life in Jesus Christ through sound preaching/teaching of His Word.

Take this important task seriously. Heaven is waiting to rejoice over every sinner who turns to God around you. Pray for those around you, share the gospel with love and guide them to Christ. Your effort would bring people to salvation and fill heaven with great joy.

PRAYER POINTS

1. Lord, help me to care deeply for the salvation of others.

2. Father, may my actions evangelistically bring joy in heaven.

3. Pray for CAC JABU, the principal officers, staff and students as led by God's Spirit.

SUGGESTED HYMN FOR TODAY:
CACGHB: 432

6 6 6 6 8 8

1. Blow ye the trumpet blow!
The gladly solemn sound
Let all the nations know,
To earth's remotest bound,
The year of jubilee is come!
Return, ye ransomed sinners, home.

2. Extol the Lamb of God,
The all-atoning Lamb;
Redemption by His blood
Throughout the world proclaim.

3. Ye, who have sold for nought
Your heritage above,
Receive it back unbought,
The gift of Jesus' love

4. Jesus our great High Priest,
Has full atonement made;
Ye weary spirits, rest;
Ye mournful souls, be glad.

5. Hearts that are weary, come
Rest on the Saviour's breast
Disconsolate heart, come
Be cheerful and rejoice.

Amen.

EXTRA READING FOR TODAY:
Jeremiah 12-14

AUTHOR
CAC, Christian Education Department.

Stay blessed and fruitful for the glory of God.

23/08/2026

ÌJỌ ÀPỌ́SÍTÉLÌ KRISTI
Naijiria àti Oke Okun

OMI IYE NAA, (January- December, 2026)

Ọjọ Aiku (Sunday), August 23, 2026.

ÀKÒRÍ:
ÈRÈ INÚ IBAṢEPỌ TI O DARA PẸLU AWỌN ỌMỌ-ẸYIN

AKỌSORI:

Nitorina bi Ọmọ ba sọ nyin di omnira, ẹ ó di omnira nitõtọ (Johanu 8:36).

KA:
Ẹksodu 3:7-10

[7]. OLUWA si wipe, Nitõtọ emi ti ri ipọnju awọn enia mi ti o wà ni Egipti, mo si gbọ́ igbe wọn nitori awọn akoniṣiṣẹ wọn; nitoriti mo mọ̀ ibanujẹ wọn;

[8]. Emi si sọkalẹ wa lati gbà wọn lọwọ awọn ara Egipti, ati lati mú wọn goke ti ilẹ na wá si ilẹ rere ati nla, si ilẹ ti nṣàn fun wàra ati fun oyin; si ibi ti awọn ara Kenaani, ati ti awọn Hitti, ati ti awọn Amori, ati ti awọn Perissi, ati ti awọn Hifi, ati ti awọn Jebusi.

[9]. Njẹ nisisiyi, kiyesi i, igbe awọn ọmọ Israeli dé ọdọ mi; emi si ti ri pẹlu, wahala ti awọn ọba Egipti nwahala wọn.

[10]. Nitorina wá nisisiyi, emi o si rán ọ si Farao, ki iwọ ki o le mú awọn enia mi, awọn ọmọ Israeli, lati Egipti jade wá.

ITUPALẸ:

Ni oni, a n wo abala ti o ṣókủnkun ninu itàn, òwò ẹru, a si n ṣe ajọyọ idádúró rẹ. A tun yipada si Ọ̀rọ̀ Olorun, nibi ti O ti ṣe afihan ijinlẹ ifẹ Rẹ fun awọn ẹni ti a n pọn loju. Ni Ẹksodu 3:7-10, Ọlọrun ṣe afihan èto Rẹ lati gba awọn ọmọ Israẹli kúrò ni Egipti. Èyi n rán wa léti pé Ọlọrun ní ifẹ si awọn ti ó n jiyà O si n pe awọn eniyan Rẹ si ojuṣe. Fifi opin si òwò ẹrú ṣe afihan ija iran eniyan fun idajọ, ṣugbọn ominira tootọ ọdọ Jesu ní o ti n wá. Eyi ni pataki Johanu 8:36. Jesu kò kàn sọ wa di ominira kúrò ninu ifiya jẹni nipa ti ara nikan: O tú wa silẹ kuro ninu ẹwọn ẹṣẹ, ibẹru, ati ainireti. Ominira Tirẹ maa n mú alaáfia pipe, ayọ ati erongba wá.

Bi a ṣe n sami ọjọ yií, ẹ jẹ ki a yẹ ọkan wa wo. Njẹ a n gbé awọn ẹrù, bii idalẹbi, iwa buburu, tabi aniyàn, ti o maa n dá wa pada sẹyin bi? Jesu n pè wa lati jọwọ gbogbo wọn fún Oun ki a si máá gbé ninu ominira tí O fún wa. O tún n pe wá lati jẹ ọwọ ati ẹsẹ oun, lati maa ran awọn ẹlomiran lọwọ lati mọ ominira. Yala nipa adura, sisọrọ jade tako idajọ èké, tabi iwa iṣoore, gbogbo igbesẹ bi o ti wu ki o kéré tó ni o máa n ni iyatọ.

Jẹ ki ọjọ oni ru wa sókè lati gbe gẹgẹ bi eniyan ti o ti di ominira kii ṣe ni ti ara nikan, ṣugbọn nipa ti ẹmi -- mímú ireti ati imúpadà
bọsipo wá fun araye.

Awọn koko Adura

1. Oluwa, O ṣeun fűn ominira ti o fi funni nipasẹ Jesu. Ràn mi lọwọ lati maa gbe ni ẹkunrẹrẹ ni oore-ọfẹ Rẹ.

2. Baba, lò mi lati mú ominira ati iwosan wá fún awọn ti o n jiyà àisi idajọ ododo.

3. Oluwa, bùkún fún gbogbo awọn ti n jà fún idajọ ododo ki O si daàbò bo awọn ti a n jẹ niya ki wọn le ṣe afihan ifẹ Rẹ.

Orin Ti A Dabaa Fun Oni: C.A.CGHB: 748

OJILELẸẸDẸGBẸRIN O LE MẸJỌ

L M

Njẹ nisisiyi, Oluwa, kini mo duro de? Ireti mi mbẹ li ọdọ Rẹ.
O. D. 39:7

1. Kili ohun ti mo nlepa?
Kini 'reti at'ife mi?
Ki ntele od'agutan na,
Ki nma lepa aworan Re.

2. Gbogbo 'reti mi mbe n'nu Re,
Pe ki ntun je eni t'O fe;
Ki nri igbala Re laye,
Ki nsi je adun Re l'oke.

3. Mo npongbe f'Oluwa iye
Ti o ku l'oke Kalfari;
F'orisun omi, on eje
Ti nti 'ha Imanuel jade.

4. Mo npongbe f'omi ife Re:
Emi ayo ti a ko mo,
Ki emi si tun mu l'oke
B'o ti nsun l'at' ori ite.

Amin.

Afikun Ibi kika Fun Oni:
Jeremáyà 6-8.

23/08/2026

CHRIST APOSTOLIC CHURCH
[Nigeria and Overseas]

THE LIVING WATER [January-December, 2026]

DAILY DEVOTIONAL GUIDE

DATE:
Sunday, 23rd August, 2026
[International Day for the Remembrance of the Slave Trade and its Abolition]

TOPIC:
BENEFITS OF GOOD RELATIONSHIP WITH SUBORDINATES

MEMORISE

Therefore if the Son makes you free, you shall be free indeed (John 8:36).

READ:
Exodus 3:7-10

[7]. And the Lord said: “I have surely seen the oppression of My people who are in Egypt, and have heard their cry because of their taskmasters, for I know their sorrows.

[8]. So I have come down to deliver them out of the hand of the Egyptians, and to bring them up from that land to a good and large land, to a land flowing with milk and honey, to the place of the Canaanites and the Hittites and the Amorites and the Perizzites and the Hivites and the Jebusites.

[9]. Now therefore, behold, the cry of the children of Israel has come to Me, and I have also seen the oppression with which the Egyptians oppress them.

[10]. Come now, therefore, and I will send you to Pharaoh that you may bring My people, the children of Israel, out of Egypt.”

EXPOSITION

Today, we reflect on a dark chapter in history, the slave trade, and celebrate its abolition. We also turn to God's Word, where He shows His deep care for the oppressed. In Exodus 3:7-10, God reveals His plan to rescue the Israelites from Egypt. This reminds us that God cares deeply about those who suffer and calls His people to action. The abolition of slavery shows humanity's fight for justice, but true freedom comes from Jesus. This is the import of John 8:36. Jesus doesn't just free us from physical oppression; He liberates us from the chains of sin, fear, and hopelessness. His freedom brings lasting peace, joy, and purpose.

As we mark this day, let us examine our hearts. Are we carrying burdens, such as guilt, bad habits, or worries, that hold us back? Jesus invites us to surrender them to Him and live in the freedom He offers. He also calls us to be His hands and feet, to help others know freedom. Whether through prayer, speaking out against injustice, or acts of kindness, every small step makes a difference.

Let this day inspire us to live as people who are free-not just physically, but spiritually -- bringing hope and restoration to the world.

PRAYER POINTS

1. Lord, thank You for the freedom You give through Jesus. Help me to live fully in Your grace.

2. Father, use me to bring freedom and healing to those who suffer injustice.

3. Lord, bless all who fight for justice and protect the oppressed. May they reflect Your love.

SUGGESTED HYMN FOR TODAY:
CACGHB: 748

L M

1. What is the thing that I long for?
What is my hope or my desire?
How I crave to follow the Lamb
And I His image to adopt.

2. All my hope, Lord on Thee is stayed
I long to be the one you love
I want to be saved here on earth
And fellowship with Thee above.

3. I hunger for the Lord of life
Who died for me on Calvary
For the source of water and blood
That from Thy wounded side which flow'd.

4. I desire Thy water of love
Spirit of joy that's yet unknown
Grant that I may yet drink above
As it does stream forth from Thy throne.

Amen.

EXTRA READING FOR TODAY:
Jeremiah 6-8

AUTHOR.
CAC, Christian Education Department.

Stay blessed and fruitful for the glory of God.

22/08/2026

ÌJỌ ÀPỌ́SÍTÉLÌ KRISTI
Naijiria àti Oke Okun

OMI IYE NAA, (January- December, 2026)

Ọjọ
Abamẹta (Saturday), August 22, 2026.

ÀKÒRÍ:
SÍSỌNÙ SÍNÚ IJỌ: OTITỌ SÍSỌNÙ GAN-AN

AKỌSORI:

Nitori Ọmọ-enia wá lati gbà awọn ti o ti nù là (Matiu 18:11).

KA:
Luku 15:8-10

[8]. Tabi obinrin wo li o ni fadaka mẹwa bi o ba sọ ọkan nù, ti kì yio tàn fitilà, ki o si gbá ile, ki o si wá a gidigidi t**i yio fi ri i?

[9]. Nigbati o si ri i, o pè awọn ọrẹ́ ati awọn aladugbo rẹ̀ jọ, o wipe, Ẹ ba mi yọ̀; nitori mo ri fadakà ti mo ti sọnù.

[10]. Mo wi fun nyin, gẹgẹ bẹ̃li ayọ̀ mbẹ niwaju awọn angẹli Ọlọrun lori ẹlẹṣẹ kan ti o ronupiwada.

ITUPALẸ:

Ìyá kan pẹlu ọmọdekunrin rẹ kan wọ ọkọ òfurufu kan ti ó kún fún ọpọlọpọ èrò. Laipẹ ti ọkọ òfurufu náà gbéra, iyá náà lọ lati ṣe igbọnṣẹ. Nigba ti o pada si ori ijókòó rẹ, kò ri ọmọ rẹ naa mọ, O wá ibi gbogbo ninu ọkọ ofurufu náà, o n bẹ awọn eniyan fun iranlọwọ. Awọn oṣiṣẹ inú ọkọ òfurufu náà tilẹ ṣe ayẹwò orukọ awọn èrò inú ọkọ náà wọn si ri pé orukọ ọmọdekunrin náà kò si nibẹ. Ṣugbọn ó dá iya náà loju pe ọmọ òun wà ninu ọkọ ofurufü náà tori pé wọn jọ wọ inú rẹ ni.

Itàn yìí n ran wa leti awọn ohun ti o n ṣẹlẹ ninu ọpọlọpọ ijọ lonii. Ọpọlọpọ a maa pejọ lati kọrin, gbadura pẹlu ijọsin. Ṣugbọn awọn kan ti sọnu ninu/niti ẹmi. Orukọ wọn ni a ko kọ sinu Iwe Iye. Wọn wà ninu awọn ti wọn n gbé lori ilẹ aye...ti a kò kọ orukọ wọn sinu Iwe Iyè ti ọdọ Aguntan ti a ti pa lati ipilẹṣẹ ayé (Ifi. 13:8). Wọn le jáfáfá ninu awọn eto inu ijọ, bi apẹẹrẹ jijẹ ọmọ ẹgbẹ akọrin tabi olukọ ile ẹkọ Ọjọ isinmi, ṣugbọn wọn kò mọ Kristi ni tòótọ́.

Ni Luku 15:8-10, fàdàkà ti o sọnu wà ninú ilé ṣugbọn a ṣi n wa a, gẹgẹ bi ọpọlọpọ eniyan ti a n ri ni ojukoojú ninu ijọ ṣugbọn ti wọn ko tii ri igbala. A gbọdọ wa wọn ki a si mú wọn tọ Kristi lọ. Gẹgẹ bi obinrin ti o wa fadákà rẹ ti o sọnu, a kò gbọdọ sinmi t**i di ìgbà ti a ba ri wọn ti a si mú wọn pada si ọdọ Kristi.

Awọn koko Adura

1. Olúwa, ṣi mi ni ojú lati ri awọn ti o ti sọnu ninu ijọ, ki O lè lò mí lati mú wọn pada sọdọ Rẹ.

2. Baba, jẹ ki oore-ọfẹ mu gbogbo ọkan ti o ti sọnu wa si igbala.

3. Jesu Olúwa, ran ijọ lọwọ lati ni ifaraji si titọka awọn ọmọ Ijọ si Ọ, Iwọ kan ṣoṣo Olúwa ati Olùgbalà wọn.

Orin Ti A Dabaa Fun Oni: C.A.CGHB: 906

ẸẸDẸGBẸRUN O LE MẸFA

11 10 11 10 11 10

Ẹ lọ wasu ihinrere fun gbogbo ẹda.
Mk. 16:15.

1. Yo awon ti nsegbe, sajo eni nku,
F'anu ja won kuro ninu ese;
Ke f'awon ti nsina gb'eni subu ro,
So fun won pe, Jesu le gba won la

Yo awon ti nsegbe, sajo eni nku,
Alanu ni Jesu, yio gbala.

2. Bi won tile gan, sibe O nduro
Lati gb'omo t'o ronupiwada
Sa f'itara ro won, si ro won jeje,
On o dariji bi won je gbagbo.

3. Ero okan eda ti esu te pa
Ni ore-ofe le tun mu pada;
Okan ti o gb'ogbe, t'a fowo ife
At'inu rere soji, y'o korin.

4. Yo awon ti nsegbe - ise tire ni,
Oluwa yio f'agbara fun o;
Fi suru ro won pada s'ona toro,
So f'asako p'Olugbala ti ku.

Amin.

Afikun Ibi kika Fun Oni:
Jeremáyà 3-5.

22/08/2026

CHRIST APOSTOLIC CHURCH
[Nigeria and Overseas]

THE LIVING WATER [January-December, 2026]

DAILY DEVOTIONAL GUIDE

DATE:
Saturday, 22nd August, 2026

TOPIC:
LOST IN THE CHURCH: THE REALITY OF BEING LOST

MEMORISE

For the Son of Man has come to save that which was lost (Matthew 18:11).

READ:
Luke 15:8-10

[8]. “Or what woman, having ten silver coins, if she loses one coin, does not light a lamp, sweep the house, and search carefully until she finds it?

[9]. And when she has found it, she calls her friends and neighbors together, saying, ‘Rejoice with me, for I have found the piece which I lost!’

[10]. Likewise, I say to you, there is joy in the presence of the angels of God over one sinner who repents.”

EXPOSITION

A mother and her young son got on a big plane filled with many passengers. Soon after the flight began, the mother went to use the restroom. When she came back to her seat, her son was missing. She searched everywhere on the plane, asking for help. The flight crew even checked the passengers list and found that her son's name was not on it. But the mother was certain her son was on the plane because they had boarded together.

This story reminds us of what happens in some churches today. Many people gather to sing, pray and worship, but some are spiritually lost. Their names are not written in the Book of Life. They are actually part of those who dwell on the earth... _whose names have not been written in the Book of Life of the Lamb slain from the foundation of the world_ (Rev 13:8). They might appear active in church activities, e.g. choir ministry or Sunday school teaching, but they do not truly know Christ.

In Luke 15:8-10, the lost coin was inside the house but still missing, just as some people are physically in church but haven't found salvation. We are to seek and lead them to Christ. Like the woman who searched for her lost coin, we mustn't give up until they are found and led back to Christ.

PRAYER POINTS

1. Lord, open my eyes to those who are lost in the Church, so that I can be used of You to lead them back to You.

2. Father, may Your grace bring every lost soul to salvation.

3. Lord Jesus, help the church to be committed to pointing the membership to You, their only Lord and saviour.

SUGGESTED HYMN FOR TODAY:
CACGHB: 906

11 10 11 10 11 10

1. Rescue the perishing, Care for the dying,
Sn**ch them in pity from sin and the grave
Weep o'er the erring one, Lift up the fallen,
Tell them of Jesus the Mighty to save,
Rescue the perishing, care for the dying;
Jesus is merciful, Jesus will save.

2. Though they are slighting Him still
He is waiting,
Waiting the penitent child to receive,
Plead with them earnestly,
Plead with them gently:
He will forgive if they only believe.

3. Down in the human heart,Crush'd by the tempter
Feelings lie buried that grace can restore:
Touch'd by a loving hand,
Waken'd by kindness,
Chords that were broken will
vibrate once more.

4. Rescue the perishing duty demands it;
Strength for thy labour the Lord will provide:
Back to the narrow way Patiently win them;
Tell the poor wand'rer a Saviour had died.

Amen.

EXTRA READING FOR TODAY:
Jeremiah 3-5

AUTHOR
CAC, Christian Education Department.

Stay blessed and fruitful for the glory of God.

20/08/2026

ÌJỌ ÀPỌ́SÍTÉLÌ KRISTI
Naijiria àti Oke Okun

OMI IYE NAA, (January- December, 2026)

Ẹti (Friday), August 21, 2026.

ÀKÒRÍ:
MÚ WỌN DÁNI/ LỌWỌ

AKỌSORI:

Mose si dide, ati Joṣua iranṣẹ rẹ̀: Mose si gòke lọ si oke Ọlọrun (Eksodu 24:13).

KA:
Ẹksodu 24:9-18

[9]. Nigbana ni Mose, ati Aaroni, Nadabu, ati Abihu, ati ãdọrin ninu awọn àgba Israeli gòke lọ:

[10]. Nwọn si ri Ọlọrun Israeli; bi iṣẹ okuta Safire wà li abẹ ẹsẹ̀ rẹ̀, o si dabi irisi ọrun ni imọ́toto rẹ̀.

[11]. Kò si nà ọwọ́ rẹ̀ lé awọn ọlọlá ọmọ Israeli: nwọn si ri Ọlọrun, nwọn si jẹ, nwọn si mu.

[12]. OLUWA si wi fun Mose pe, Gòke tọ̀ mi wá sori òke, ki o si duro nibẹ̀; emi o si fi walã okuta fun ọ, ati aṣẹ kan, ati ofin ti mo ti kọ, ki iwọ ki o le ma kọ́ wọn.

[13]. Mose si dide, ati Joṣua iranṣẹ rẹ̀: Mose si gòke lọ si oke Ọlọrun.

[14]. O si wi fun awọn àgba na pe, Ẹ duro dè wa nihinyi, t**i awa o fi tun pada tọ̀ nyin wá: si kiyesi i, Aaroni ati Huri mbẹ pẹlu nyin: bi ẹnikan ba li ọ̀ran kan, ki o tọ̀ wọn wá.

[15]. Mose si gòke lọ sori òke na, awọsanma si bò òke na mọlẹ.

[16]. Ogo OLUWA si sọkalẹ sori òke Sinai, awọsanma na si bò o mọlẹ ni ijọ́ mẹfa: ni ijọ́ keje o ké si Mose lati ãrin awọsanma wá.

[17]. Iwò ogo OLUWA dabi iná ajonirun li ori òke na li oju awọn ọmọ Israeli.

[18]. Mose si lọ sãrin awọsanma na, o sì gùn ori òke na: Mose si wà lori òke li ogoji ọsán ati ogoji oru.

ITUPALẸ:

Ọjọ Awọn Àgbààgbà Lágbàyé n ran wa leti lati maa bu ọla fún ọgbọn awọn àgbàlagbá nigba ti a bá n pèsè awọn ọdọ silẹ lati dipò aṣáájú. Jijẹ olori kii ṣe nipa p**a aṣẹ nikan; o jẹ titọ awọn eniyan sọna ki a si jẹ ki wọn kópa ninu irin ajo naa. Oye eyi yé Mose pẹlu. Nigba ti ó n lọ lati pade Ọlọrun, kò lọ ni òun nikan; ó mú awọn àgbà ati olùrànlọwọ rẹ, Joṣua pẹlu rẹ. Nigba ti awọn àgbààgbà wà lẹyin, Joṣua tẹ siwaju pẹlu Nose lati fi oju ri iwalaaye Ọlọrun.

IIana yii ṣe afihan pataki kikọ ati pipese silẹ awọn ti yoo maa tẹsiwaju iṣẹ naa lẹyin wa. A le kọ́ iṣẹ ṣugbọn ti awọn olori ni ọjọ ọla ko ba ni oye igbagbọ, adura, tàbi ifaraji nipa ti ẹmi, ó lè má rọrun fun wọn lati tẹsiwaju ninu iṣẹ naa. Mose tọ Joṣua sọna nipa mimu un wa sinu iriri ijinlẹ ti iwaláàyè Ọlọrun.

Jesu pẹlu ṣe ohun ti o dà bí eyi. Ni awọn àkókò ti o ṣe pataki, bii ni akoko adura Rẹ ni Getsemane, Ó mú awọn ọmọ ẹyin Rẹ ti o sún mọ lọwọ lọ. Fifi oju ri bi Jesu ṣe jọsin to ran wọn lọwọ lati pèsè wọn silẹ lati gbe pẹlu Igbagbọ lẹyin ti O gòkè lọ si ọrun.

Yala o jẹ olori, olukọni, obi, tabi atọnisọna, mu awọn mìíràn pẹlu rẹ ninu irin àjò rẹ. Jẹ ki wọn kopa ninu adura ati iṣẹ isin, maa kọ wọn ni awọn ohun amuyẹ ti yoo gbe iṣẹ Ọlọrun ró. Ni ọjọ kan, awọn náà yóò tẹsiwaju ni ọna ti o ti la silẹ fún wọn.

Awọn koko Adura

1. Olúwa, dariji mi fún awọn àkókò ti mo fi nikan ṣiṣẹ, ti mo gbàgbé lati pèsè awọn ẹlomiran silẹ fun ọjọ ọla.

2. Baba, fun awọn olori wa ni ọgbọn lati mọ awọn ti ó tọ lati máá mú lọwọ.

3. Oluwa, ran wá lọwọ lati fi ọgbọn ṣe gbigbé ijọba tuntun kalẹ lẹyin ti ọkan bá ti pari, ki a si lè ri daju pé iṣẹ Rẹ n tẹsiwaju lati iran kan si òmíràn.

Orin Ti A Dabaa Fun Oni: C.A.CGHB: 561

ỌTALELẸẸDẸGBẸTA O LE KAN

7 7 7 7

Iwọ ki iṣe ẹru mọ biko ṣe ọmọ.
Gal. 4:7

1. Ewe ti Oba orun
Korin didun b'e ti nlo;
Korin 'yin Olugbala,
Ologo n'nu ise Re

2. A nlo s**o Olorun
L'ona t'awon Baba rin;
Won si nyo nisisiyi,
Ayo won l'awa o ri.

3. Korin agbo kekere,
E o simi n'ite Re;
Ib'a pese 'joko yin,
Ibe si n'Ijoba yin.

4. Woke, Omo imole
Ilu Sion wa lokan;
Ibe n'ile wa t**i,
Ibe l'a o r'Oluwa.

5. Ma sa, e duro l'ayo,
Ni eti ile ti yin;
Kristi Omo Baba nwi
Pe, Laifoya k'a ma lo

6. Jesu, a nlo l'ase Re,
A ko 'hun gbogbo sile
Iwo ma j' Amona wa
A o si ma ba O lo.

Amin.

Afikun Ibi kika Fun Oni:
Isaiah 66; Jeremáyà 1-2

Address

Ibadan
200126

Website

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when CAC Living Water Daily Devotional posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Shortcuts

Share