24/05/2026
*IGBE AYE OMO LEYIN (NBC YORUBA)*
*MAY 24,2026: ỌSẸ KẸRIN*
*DÍDÈNÀ ÌWÀ-IPÁ NÍNU ILE*
*Orin: (YBH 337) Mo Ti Ṣèlérí Jesu*
*Bíbélì Kíkà: Jakọbu 4:7-12*
*Ìlànà Ìkọ́ni: Ìjọ̀rọ̀*
*Àbájáde Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Àtọ́ka:* Àwọn ọmọ Ìjọ yoo mọ ọ̀nà tí o dara jùlọ láti dènà ìwà-ipá nínú ilé, wọn yoo sì mọ̀ ọ̀nà láti nípá:
I. Mímẹ́nu bà díẹ̀ nínú àwọn ọ̀nà tí a lè dènà ìwà-ipá nínú ilé;
II. Ṣíṣe àlàyé nìṣókí lórí ètò Ọlọ́run fún ìgbéyàwó;
III. Ṣíṣe ìfarajìn ara ẹni láti dènà ìwà-ipá nínú ìdílé wọn.
*ÀKÓKÓ ÌFARAKINRA*
Olúṣọ́-àgùntàn Ìjọ kan fìwé pe ọ̀kan lára àwọn ọmọ Ìjọ rẹ̀, tí o jẹ́ ẹni tí o fọwọ́ kọ sẹ́yìn nítorí ìwà-ipá inú ilé, sí ọ́fíìsì rẹ̀ fún ìmọ̀ràn. Ó béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ bí o ṣe borí àwọn ìpọ́njú ìgbà gbogbo àti l lílo tí ọkọ rẹ̀ maa n lò ó. Obìnrin naa sọ pe, "Mo ti kọ́ láti maa ní sùúrù àti láti maa gbàdúrà sí i. Sí ògo Ọlọ́run, ọkọ mi ti n yípadà. Mo nìrétí pe yoo dara sí i lọ́jọ́ kan." Bí o bá jẹ́ pe, ìwọ ni olúṣọ́- àgùntàn Ìjọ naa, báwo ni wa a ṣe gba obìnrin yí nímọ̀ràn àti àwọn tọkọtaya míràn tí wọn maa n já loorekoore, tí wọn a sì tún máa lo onírúurú ohun ìjà nínú èdè-àìyedè tí ko to nkan?
*Ọ̀rọ̀ Ìṣípàdé Olùdarí Ẹ̀kọ́*
Lónìí, a o maa jíròrò lórí àwọn oríṣiríṣi ọ̀nà tí àwa onígbàgbọ́ lè gba dènà ìwà-ipá inú ilé láàrin tẹ̀gbọ́n -tàbúrò, tọkọ-taya àti àwọn mọ̀lẹ́bí míràn. Èyí ni pe, a o maa jíròrò lórí díẹ̀ nínú àwọn ọ̀nà tí àwa ọmọ-lẹ́yìn Kristi lè gba láti fi dènà ìwà-ipá inú ilé. Nínú Luku 12:47-48, Jesu Kristi tọ́ka sí ọ̀rọ̀ òtítọ́ kan to dájú pe ìránṣẹ́ kan tí o mọ̀ ìfẹ́ olúwa rẹ̀ tí o sì kọ láti ṣe e, ní a o nà púpọ̀, nìgbà tí èyí tí ko mọ̀ ohun tí olúwa rẹ̀ fẹ́, tí o sì ṣe èyí tí o yẹ sí lùlù ní a o nà níwọ̀nba. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run han kédere nípa àwọn nnkan tí a lè yàgò fún tí o lè fa ìwà-ipá nínú ilé. Ìwé Mímọ́ sọ pe ẹni tí o mọ ohun tí o yẹ kí o ṣe, tí kọ̀ sẹ́ ẹ, tí dẹ́sẹ̀. Ní wíwoye nípa Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹ̀kọ́ ti oní ní yoo sọrọ nipa awọn ohun ti a nilo lati mọ ki a ma ba a lugbadi iwa-ipa ninu ile.
*AKOKO ẸKỌ/IFIKUNLUKUN*
*A. AWỌN ỌNA LATI DENA IWA-IPA NINU ILE*
Iwa-ipa kii ṣẹlẹ lai nidii. Nini oye nipa awọn ohun ti o n fa a yoo ran wa lọwọ lati le tọka si awọn ọna lati dena wọn. A ti ṣayẹwo awọn ohun ti o n fa a ni ibẹrẹ oṣu yii, nitori naa ẹ jẹ ki a wo diẹ lara awọn ọna ti a le gba dena rẹ.
*▪︎ Da orisun rẹ gan an mọ (Ẹṣu):* Ẹṣu ni ọta awa onigbagbọ ti o ga julọ. O maa n da awọn eniyan riba-ribo lọna to yatọ sira wọn, o si maa n fa iporogan laarin tọkọ-taya ati tẹgbọn-taburo ninu ile. Nitori naa, awa ọmọ-lẹyin Jesu gbọdọ ni oye eyi, ki a si dẹkun lati maa gbẹsan nigba ti wọn ba ṣẹ wa. Fifi buburu san buburu yoo kan tẹ ifẹ ọkan ẹṣu lọrun fun iwa-ipa lasan ni. Aposteli Pọọlu wi pe, "Njẹ nitori naa, ki awa ki o maa lẹpa ohun tii ṣe ti alaafia, ati ohun ti awa yoo fi gbe ara wa ró" (Romu 14:19).
*▪︎ Adura:* Ko si iṣoro ti o kọja idasi Ọlọrun. Nigba ti wahala ba n rugbo bọ ninu ile, a gbọdọ tete pinnu lati wa oju Ọlọrun ninu adura fun ọna abayọ. A gbọdọ wa oju Ọlọrun fun imọ ati ọgbọn ki o ma ba a yọri si iwa-ipa. A ni lati gbadura nipa ohun gbogbo ati ohunkohun ninu ile.
*▪︎ Gbiyanju itọju to dọgba laarin awọn tẹgbọn-taburo:* Awa obi ti a jẹ Kristiani ko gbọdọ faaye gba iwa ojuṣaju ni awọn ọna ti a n gba lati tọju awọn ọmọ wa ati awọn mọlẹbi miiran. O yẹ ki ọrọ yii naa kan awọn ti a ti gba lati maa ran wa lọwọ ninu ile (ọmọ ọdọ). Bi o tilẹ jẹ pe awọn idi kan le wa lati ṣe bẹ ẹ, o yẹ ki a lo ọgbọn ki o ma ṣe si ẹnikẹni ti a o huwa aidara si.
*▪︎ Yago fun ọrọ odi/Pipẹgan:* Ohun kan ti o le tete ṣokunfa iwa-ipa ni awọn ẹsun eke. Igbiyanju lati fi ailẹbi ẹni mulẹ le yọri si iwa-ipa. Nitori naa, awa Kristiani gbọdọ kọ lati maa sọ otitọ nigba gbogbo ki a ma si pẹgan tabi tan iroyin eke kaakiri nipa awọn eniyan miran.
*▪︎ Irẹra-ẹni-silẹ:* Idahun pẹlẹ maa n yi ibinu pada, gẹgẹ bi Iwe Mimọ ṣe sọ (Owe 15:1). Onirẹlẹ eniyan kan ko ni maa jiyan tabi maa ja nitori pe o fẹ lati fidi aijẹbi nipa ọrọ kan mulẹ.
Iru eniyan bẹẹ yoo yiju si ọdọ Ọlọrun fun iranlọwọ laarin laasigbo ati rogbodiyan naa dipo biba awọn miiran ja.
*▪︎ Suuru:* Wọn wi pe, ṣuuru ni baba iwa. Ọpọlọpọ wahala ati idaamu ti n bẹ ninu idile kan, ni iba ti ṣẹ e yago fun bi awọn eniyan ba mu ṣuuru. Awa onigbagbọ ko gbọdọ tete maa binu, bi o ti wu ki ẹṣẹ naa tobi to. A gbọdọ maa ni ṣuuru pẹlu ara wa ninu ibasepọ wa ki a si gbẹkẹle Ọlọrun lati mu iyipada ti a n pongbe fun jade ninu igbe-aye mọlẹbi ti o ṣoro lati ba gbe ti n bẹ ni ayika wa.
*▪︎ Ikora-ẹni-nijanu:* Ikora-ẹni-nijanu jẹ amuyẹ ti o lagbara ti o n ranni lọwọ lati kapa imọlara, ifẹ-ọkan ati ipongbẹ ẹni. O jẹ agbara lati kapa ara ẹni, o si ti fidi mulẹ gẹgẹ bi ọkan ninu ọna ti a le fi dena iwa-ipa.
*▪︎ Idarijin:* Idarijin jẹ aporo kan fun iwa-ipa ninu ile. Ọkan ti o ba ti kọ lati maa darijin ko ni maa wa ọna lati gbẹsan pẹlu iwa-ipa fun ẹṣẹ yoowu ti wọn ba ṣẹ ẹ.
*▪︎ Igbe-aye to kunju oṣuwọn:* Ọlọrun n reti ki awa ọmọ Rẹ gbe igbe-aye to yẹ pẹlu ara wa, paapaa julọ gẹgẹ bi ẹbi. A gbọdọ nifẹẹ ara wa, ki a gbadura, ki a si wa ire eniyan gbogbo dipo rogbodiyan, ikoriira, owu, ati aigbọra ẹni ye.
*Akoko Ijiroro:* Awọn ọna miiran wo ni a tun le gba dena iwa-ipa inu ile?
*B. ETO ỌLỌRUN FUN IGBEYAWO/ IDILE*
Iwe Gẹnẹsisi sọ fun wa pe Ọlọrun ni Oludasile igbeyawo. Lẹyin ti Ọlọrun ti da ohun gbogbo tan, ti o fi mọ eniyan, O ri i pe Adamu ko ni oluranlọwọ. O wa wi pe, “kò dara ki ọkunrin naa ki o nikan maa gbé; Emi yoo ṣe oluranlọwọ ti o dabi rẹ fun un.” O si mu orun ijika kùn ọkunrin naa, o si sùn: O si yọ ọkan ninu egungun-iha rẹ, O si fi egungun-iha ti O mu ni iha ọkunrin naa mọ obinrin, O si mu un tọ Adamu wá. (Gẹnẹsisi 2:18, 21-22). Adamu fi tayọtayọ da a mọ pe Efa ri bi oun tikara rẹ ati pe a da wọn lati maa gbe papọ ni. Nígbà gbogbo, a da obinrin yii lati jẹ alabàṣepọ, ọrẹ, ati oluranlọwọ ọkunrin naa. Ṣugbọn, Adamu ati Efa fi tayo-tayo gbepọ gẹgẹ bi ọkọ ati aya t**i di igba ti ẹṣu tan obinrin naa lati jẹ eso to jẹ eewọ fun wọn. Ṣibe-ṣibẹ, ọrọ ti a pe ni “oluranlọwọ” ko tumọ si pe obinrin naa ko jámọ nkan kan tabi pe ẹru ni si ọkunrin naa. Nitori níbí ni àkọsílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú àwòrán yí ní ètò bí i ti ìwé kíkà:
naa, o jẹ ojuse ọkunrin lati maa bikita fun iyawo rẹ gẹgẹ bi o ṣe n bikita fun ara rẹ. Aposteli Pọọlu ṣalaye eyi gbangba-gbangba ninu lẹta rẹ si Ijọ Efesu nigba ti o wi pe, "Ẹyin ọkọ, ẹ fẹran awọn iyawo yin, gẹgẹ bi Kristi si ti fẹran ijọ, ti o si fi ara Rẹ fun un. Ki Oun kọ o le sọ ọ di mimọ lẹyin ti a ti fi ọrọ wẹ ẹ mọ ninu agbada omi. Bẹẹni o tọ ki awọn ọkunrin ki o maa fẹran awọn iyawo wọn gẹgẹ bi ara awọn tikarawọn. Ẹni ti o ba fẹran aya rẹ, o fẹran oun tikararẹ. Nitori kò si ẹnikan ti o ti korira ara rẹ; bikọṣe pe ki o maa bọọ ki o si maa ṣike rẹ gẹgẹ bi Kristi si ti n ṣe si ijọ" (Efesu 5:25-29). Àwọn yii ni ipilẹ idile onigbagbọ to bojumọ ti ko ni iwa-ipa ninu. Awọn ilana wọnyi ni eto Ọlọrun fun igbeyawo.
*▪︎ Ibikita:* A reti pe ki awọn ẹbi bikita, ki wọn si kiyesi ara wọn ni gbogbo ọna. Nigba ti eyi ba di șișe, ko ni si aaye fun iwa-ipa inu ile dipo bẹẹ, a o maa yanju awọn ọrọ ti o ba suyo ni tubi-n-nubi laisi ikorira si ara wọn.
*▪︎ Ife:* Ifẹ jẹ nkan pataki ninu ile ti o le din ipele ikoro laarin mọlẹbi ku. O maa n mu ifẹ, ibikita, ati iwuri dagba ninu idile, eyi si yẹ ki o jẹ ojuse gbogbo eniyan.
*▪︎ Igbọran:* Iwe Efesu gba awọn ọmọ niyanju lati maa gbọran ki wọn si maa bọwọ fun awọn obi wọn ninu Oluwa, ki awọn ẹru naa maa gbọran si awọn oluwa wọn lẹnu (Ẹksodu 20:12, Efesu 6:1,5-6).
*▪︎ Iteriba:* Awọn tọkọtaya gbọdọ maa teriba fun ara wọn lati ọwọ ti wọn ni fun Kristi. Ọlọrun n reti pe itẹriba yoo raaye ninu ibasẹpọ eniyan gbogbo, ọkọ/aya, awọn ọmọ/awọn obi, ẹru/oluwa lati gbe ni alaafia ati ni ibamu pẹlu eto Ọlọrun fun idile.
Iṣọkan: Ẹnikan sọ nigba kan ri pe, "idile to wa ni iṣọkan jẹ idile to n tẹsiwaju." Onisaamu wi pe, "Kiyesi i, o ti dara o si ti dùn to fun awọn ará lati maa jumọ gbe ni iẹpọ” (Orin Dafidi 133:1). Ọlọrun n reti pe ki ẹbi maa gbe ni alaafia ati ni irepọ bi o ti wu ki a yatọ si ara wọn to.
Bi a ba tẹle awọn ilana wọnyi, awọn idile wa yoo dabi ọrun lorilẹ aye, Ọlọrun yoo si di ayinlogo.
*Akoko Ijiroro:* Șẹ alaye pẹlu awọn itọkasi lati inu Bibeli iyatọ to wa laarin itẹriba fun ọkọ/aya ẹni ati jije ọjọ
Ọ̀rọ̀ Ìparí Olùdarí Ẹ̀kọ́
Òjulówó ètò Ọlọ́run fún ìdílé kò ní eyìkeyí ìwà-ipá láàrin mọ̀lẹ́bí ninu láìka ìpele ìmunibínú yòówù sí. Nígbà gbogbo ni ìdúró sinsin ìdílé àti àwùjọ jẹ́ Ọlọ́run lógún láti ìgbà tí Ó ti mú Adamu àti Efa wá papọ̀ nínú ìṣọ̀pọ̀ ìgbéyàwó. Nítorí náà, àwọn ìgbéyàwó Kristiani kò gbọ́dọ̀ bàjẹ́ nítorí ìwà-ipá nínú ilé, gẹ́gẹ́ bí a ti rí i nínú àwọn ìdílé kan lónìí. Nígbà tí ẹnìkan mejì bá ṣe ìgbéyàwó, a retí kí wọn farajìn fún ara wọn, kí wọn ṣè-àtìlẹyìn, kí wọn sì bíkítà fún ara wọn, kí wọn sì jẹ́ ọ̀rẹ́ tò dára jùlọ fún ara wọn. Bí ò tilẹ̀ jẹ́ pé, kò sí ìdílé tí kò ní ìpèníjà kankan, nígbà tí tọkọtaya àti àwọn mọ̀lẹ́bí yòókù bá farajìn fún ara wọn lóòótọ́, ìfẹ́ òtítọ́ yoo farahàn nínú ilé, àlàáfíà yoo sì tẹ̀síwájú láti máa jọba. Àwọn ọmọ-lẹ́yìn Kristi gbọ́dọ̀ mọ̀ pé lẹ́tarí àwọn ìyàtọ̀ wa, àwọn aawọ̀ kan lè ṣẹlẹ̀ láàrin mọ̀lẹ́bí, ṣùgbọ́n a kò gbọ́dọ̀ gba àyè láti burú de ìkorìta ṣíṣokùnfà ìwà-ipá lẹ́tarí àwọn àtubọ̀tán rẹ̀ lórí àwọn òbí àti àwọn ọmọ. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú ìdílé lé pinnu láti má lọ́wọ́ nínú ohun yòówù tí yoo yọrí sí ìwà-ipá, láìfí ti ìmunibínú ṣe. Níbí tí ìwà-ipá bá ti ń ṣẹlẹ̀ nígbà gbogbo, a lè béèrè fún ìrànlọ́wọ́ láti inú Ìjọ Ọlọ́run tàbí olùdámọ̀ràn nípa ìgbéyàwó tí ò jẹ́ Kristiani tí wọn mọ̀ mọ̀ wá ọ̀nà àbáyọ tò múnádóko tí ò sì wúlò.
*Àdúrà:* Gbadura pe Ọlọ́run yoo sọ ọ́ di ohun elo àlàáfíà nínú ìdílé, Ìjọ Ọlọ́run àti ní àwùjọ rẹ.
*Ìṣe Ṣíṣe Lẹ́yìn Ẹ̀kọ́*
Mọ̀-ọ́n-mọ̀ gbé ìgbésẹ̀ ní ọ̀sẹ̀ yìí láti dẹ́ ọ̀dọ́ ìpín kékeré kan níbi tí a ò ti lè jíròrò nípa ẹ̀kọ́ tí oní fún ànfààní àwọn tí o ń kojú ìpèníjà ìwà-ipá nínú ilé.