ECWA Church Anglo-Jos, Plateau State

ECWA Church Anglo-Jos, Plateau State Welcome to the official page of ECWA Anglo-Jos. Follow us for Bible teachings, Church events, Sermons and fellowship. God bless you!

07/08/2026

ỌJỌ́ ẸTÌ (FRIDAY),
7 AUGUST, 2026
Kíkọ Nínú Ìwé Orin ECWA: EHB 482
IBI KÍKÀ: ÌFIHÀN 12:10-17
KÓKÓ ẸKỌ: ÀJỌYỌ PÉ ALÉ OLÙFISÙN KÚRÒ NÍ ỌRUN

ÌFIHÀN 12:10-17

10 Mo si gbọ́ ohùn rara li ọrun, nwipe, Nigbayi ni igbala de, ati agbara, ati ijọba Ọlọrun wa, ati ọla ti Kristi rẹ̀; nitori a ti lé olufisùn awọn arakunrin wa jade, ti o nfi wọn sùn niwaju Ọlọrun wa lọsán ati loru.

11 Nwọn si ṣẹgun rẹ̀ nitori ẹ̀jẹ Ọdọ-Agutan na, ati nitori ọ̀rọ ẹrí wọn, nwọn kò si fẹran ẹmi wọn ani t**i de ikú.

12 Nitorina ẹ mã yọ̀, ẹnyin ọrun, ati ẹnyin ti ngbé inu wọn. Egbé ni fun aiye ati fun okun! nitori Èṣu sọkalẹ tọ̀ nyin wá ni ibinu nla, nitori o mọ̀ pe ìgba kukuru ṣá li on ni.

13 Nigbati dragoni na ri pe a lé on lọ si ilẹ aiye, o ṣe inunibini si obinrin ti o bí ọmọkunrin na.

14 A si fi apá iyẹ́ meji ti idì nla na fun obinrin na, pe ki o fò lọ si aginjù, si ipò rẹ̀, nibiti a gbé bọ́ ọ fun akoko kan ati fun awọn akoko, ati fun idaji akoko kuro lọdọ ejò na.

15 Ejò na si tú omi jade lati ẹnu rẹ̀ wá bi odo nla sẹhin obinrin na, ki o le mu ki ìṣan omi na gbá a lọ.

16 Ilẹ si ràn obinrin na lọwọ, ilẹ si yà ẹnu rẹ̀, o si fi ìṣan omi na mu, ti dragoni na tú jade lati ẹnu rẹ̀ wá.

17 Dragoni na si binu gidigidi si obinrin na, o si lọ ba awọn iru-ọmọ rẹ̀ iyokù jagun, ti nwọn npa ofin Ọlọrun mọ́, ti nwọn si di ẹrí Jesu mu.

ÀJỌYỌ PÉ ALÉ OLÙFISÙN KÚRÒ NÍ ỌRUN

Ayé wá kún fún ìrora àti ìbànújẹ́ èyí tí Sátánì àti àwọn ẹ̀mí òkùnkùn rẹ̀ ṣe okùnfà rẹ̀. Ìròyìn búburú wà ní ibi gbogbo, ó sì ti mọ́ àwọn ènìyàn lára toríopé wọn tí yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run.

Láìsí Ọlọ́run, Èṣù ni eniyan a súnmọ́. Kò ya ọ̀pọ̀ àwọn adaríwa lẹ́nu níti àwọn ìsẹ̀lẹ̀ náà. Bí wọn ti ń bá àwọn ẹgbẹ́ bí Boko Haram àti Awọn ajínigbé jà, wọ́n tún dákún ìṣòro náà nípa jíjìnnà sì àwọn ẹ̀kọ́ Ọlọ́run.

Èṣù ti tan ọ̀pọ̀ jẹ. Kò yani lẹ́nu pé àwọn áńgẹ́lì ń yọ̀ ní ọ̀run nígbà tí a le Sátánì sì ayé (ẹsẹ 10-11), lékè gbogbo ìkìlọ̀, “ègbé ni fún àwọn olùgbé ayé” (ẹsẹ 10-12).

ÌBÉÈRÈ:
Kíni o lè ṣe láti dá ìkọlù Drágónì dúró lórí ìran ènìyàn?

ÀDÚRÀ:
Olúwa, jẹ́ kí iná ìjèrè-ọkàn máa jò nínú mi, kí O sì rànmí lọ́wọ́ láti pín ìyìnrere ìgbàlà pẹ̀lú gbogbo ẹni tí mo bá bá pàdé ní orúkọ Jésu, Àmín.

ÓÙNJẸ ÒÒJỌ́

06/08/2026

ỌJỌ́BỌ (THURSDAY),
6 AUGUST, 2026
Kíkọ Nínú Ìwé Orin ECWA: EHB 481
IBI KÍKÀ: ÌFIHÀN 12:1-9
KÓKÓ ẸKỌ: ÌYANU OBÌNRIN TÓ Ń RỌBÍ PẸ̀LÚ ỌMỌ ÀTI DRAGONI NÁÀ

ÌFIHÀN 12:1-9

1 ÀMI nla kan si hàn li ọrun; obinrin kan ti a fi õrùn wọ̀ li aṣọ, oṣupa si mbẹ labẹ ẹsẹ rẹ̀, ade onirawọ mejila si mbẹ li ori rẹ̀:

2 O si lóyun, o si kigbe ni irọbi, o si wà ni irora ati bimọ.

3 Àmi miran si hàn li ọrun; si kiyesi i, dragoni pupa nla kan, ti o ni ori meje ati iwo mẹwa, ati adé meje li ori rẹ̀.

4 Ìru rẹ̀ si wọ́ idamẹta awọn irawọ, o si ju wọn si ilẹ aiye, dragoni na si duro niwaju obinrin na ti o fẹ bímọ, pe nigbati o ba bí, ki o le pa ọmọ rẹ̀ jẹ.

5 O si bí ọmọkunrin kan ti yio fi ọpá irin ṣe akoso gbogbo awọn orilẹ-ède: a si gbà ọmọ rẹ̀ lọ soke si ọdọ Ọlọrun, ati si ori itẹ́ rẹ̀.

6 Obinrin na si sá lọ si aginjù, nibiti a gbé ti pèse àye silẹ dè e lati ọwọ́ Ọlọrun wá, pe ki nwọn ki o mã bọ́ ọ nibẹ̀ li ẹgbẹfa ọjọ o le ọgọta.

7 Ogun si mbẹ li ọrun: Mikaeli ati awọn angẹli rẹ̀ ba dragoni na jàgun; dragoni si jàgun ati awọn angẹli rẹ̀.

8 Nwọn kò si le ṣẹgun; bẹ̃ni a kò si ri ipo wọn mọ́ li ọrun.

9 A si lé dragoni nla na jade, ejò lailai nì, ti a npè ni Èṣu, ati Satani, ti ntàn gbogbo aiye jẹ, a si lé e jù si ilẹ aiye, a si le awọn angẹli rẹ̀ jade pẹlu rẹ̀.

ÌYANU OBÌNRIN TÓ Ń RỌBÍ PẸ̀LÚ ỌMỌ ÀTI DRAGONI NÁÀ

Ibi kíkà ti òní kún fún àpèjúwe obìnrin, ọmọ rẹ̀ àti Dragoni náà.

Ọ̀pọ̀lọ̀pọ̀ ìtumọ̀ ló wà, ṣùgbọ́n mo faramọ́ èyí ti Gary Cohen àti Salem Kirban ṣàlàyé pé Obìnrin náà dúró gẹ́gẹ́ bí ilé Ísírẹ́lì tí ọmọ rẹ̀ sì jẹ́ Kristi Mèsáyà.

Dragoni dúró bí Sátánì tí ó ń gbógun ti obìnrin náà tí ó sì ń mú ìrora wá lákókò ìbímọ rẹ̀ (ẹsẹ 3-4).

Ẹsẹ ìkẹfà dé ẹsẹ ìkẹ́sán ṣe àfihàn bí Sátánì àti àwọn áńgẹ́lì rẹ̀ ṣe di lílé kúrò ní ọ̀run lẹ́yìn ogún tó ṣẹlẹ̀ ní ọ̀run èyí tó yọrí sí ìfarahàn àwọn ẹ̀mí èṣù.

Nígbàtí ọ̀run ń yọ̀ (ẹsẹ 10-12), ayé ń jìyà. Àwọn tí ó bá súnmọ́ Jésù, ọmọ-ènìyàn ni yóò borí.

ÌBÉÈRÈ:
Ǹjẹ́ òń múrasílẹ̀ fún ìpadàbọ̀ Jésù àbí Ejò àtijọ́ nì àti àwọn áńgẹ́lì rẹ̀

ÀDÚRÀ:
Rànmí lọ́wọ́ Ọlọ́run láti múrasílẹ̀ fún bíbọ̀ Rẹ kì O sì sọ́ mi láti tẹ̀lé Ọ ní gbogbo ìgbà ní orúkọ Jésù, Àmín.

ÓÙNJẸ ÒÒJỌ́

05/08/2026

ỌJỌ́RÚ (WEDNESDAY),
5 AUGUST, 2026
Kíkọ Nínú Ìwé Orin ECWA: EHB 480
IBI KÍKÀ: ÌFIHÀN 11:15-19
KÓKÓ ẸKỌ: ÁNGẸLÌ KEJE FỌN ÌPÈ TI RẸ

ÌFIHÀN 11:15-19

15 Angẹli keje si fun ipè; a si gbọ́ ohùn nla lati ọrun wá, wipe, Ijọba aiye di ti Oluwa wa, ati ti Kristi rẹ̀; on o si jọba lai ati lailai.

16 Awọn àgba mẹrinlelogun nì ti nwọn joko niwaju Ọlọrun lori ítẹ wọn, dojubolẹ, nwọn si sìn Ọlọrun,

17 Wipe, Awa fi ọpẹ́ fun ọ, Oluwa Ọlọrun, Olodumare, ti mbẹ, ti o si ti wà, ti o si ma bọ̀; nitoriti iwọ ti gbà agbara nla rẹ, iwọ si ti jọba.

18 Inu si bi awọn orilẹ-ède, ibinu rẹ si de, ati ìgba lati dá awọn okú lẹjọ, ati lati fi ere fun awọn iranṣẹ rẹ woli ati awọn enia mimọ́ ati awọn ti o bẹ̀ru orukọ rẹ, ati ẹni kekere ati ẹni nla; ati lati run awọn ti npa aiye run.

19 A si ṣí tẹmpili Ọlọrun silẹ li ọrun, a si ri apoti majẹmu ninu tẹmpili rẹ̀: mànamána si kọ, a si gbọ ohùn, ãrá si san, ìṣẹlẹ si ṣẹ̀, yinyín nla si bọ.

ÁNGẸLÌ KEJE FỌN ÌPÈ TI RẸ

Ìpè keje ṣe àfihàn àjọyọ̀ dípò ìdájọ́ (15-17).

Ohùn ní ọ̀run ṣe àlàyé pé ìjọba ti ayé yí jẹ́ tí Jésù, èyí pè fún ìjọsìn àwọn àgbà (15-16).

Ìwà ibi àwọn ènìyàn fà wọ́n lọ sí inú ìbínú tí ó sì mú kí ìdájọ́ Ọlọ́run yára kánkán (ẹsẹ 17-19).

ÌBÉÈRÈ:
Ǹjẹ́ a lè rí ìwà ibi ní ọkàn àwọn ènìyàn bí? Kíni kí àwọn onígbàgbọ́ gbàdúra fún?

ÀDÚRÀ:
Fúnmi ní oore-ọ̀fẹ́ láti lè faradàá, Ọlọ́run, láti sìn Ọ́ pẹ̀lú òtítọ́ ní orúkọ Jésù, Àmín.

ÓÙNJẸ ÒÒJỌ́

04/08/2026

Well spoken Sir!

04/08/2026
Highlights of ECWA Youth week conclusion  Church Anglo-Jos, Plateau State 2/08/2026
02/08/2026

Highlights of ECWA Youth week conclusion Church Anglo-Jos, Plateau State 2/08/2026

02/08/2026

Sunday Service Church Anglo-Jos, Plateau State

SUNDAY, 2 AUGUSTTEXT: REVELATION 9:13-21TOPIC: JUDGMENT FROM THE SOUND OF THE ANGELREVELATION 9:13-21 (NIV)13: The sixth...
02/08/2026

SUNDAY, 2 AUGUST
TEXT: REVELATION 9:13-21
TOPIC: JUDGMENT FROM THE SOUND OF THE ANGEL

REVELATION 9:13-21 (NIV)

13: The sixth angel sounded his trumpet, and I heard a voice coming from the horns of the golden altar that is before God.

14: It said to the sixth angel who had the trumpet, “Release the four angels who are bound at the great river Euphrates.”

15: And the four angels who had been kept ready for this very hour and day and month and year were released to kill a third of mankind.

16: The number of the mounted troops was two hundred million. I heard their number.

17: The horses and riders I saw in my vision looked like this: Their breastplates were fiery red, dark blue, and yellow as sulfur. The heads of the horses resembled the heads of lions, and out of their mouths came fire, smoke and sulfur.

18: A third of mankind was killed by the three plagues of fire, smoke and sulfur that came out of their mouths.

19: The power of the horses was in their mouths and in their tails; for their tails werended e snakes, having heads with which they inflict injury.

20: The rest of mankind that were not killed by these plagues still did not repent of the work of their hands; they did not stop worshiping demons, and idols of gold, silver, bronze, stone and wood—idols that cannot see or hear or walk.

21: Nor did they repent of their murders, their magic arts, their sexual immorality or their thefts.

JUDGMENT FROM THE SOUND OF THE ANGEL

The sixth angel sounded his trumpet signaling a serious event.

A voice from the golden altar instructed to release four angels previously restrained from harming the earth (see 7:1-3).

This moment represents a call for judgment on the wicked who have failed to seek God, as Mercy has ended (vs.13-15).

With global conflicts like Russia-Ukraine and Iran-Israel, could this foreshadow tribulation? John witnessed a massive army of two hundred million horsemen (vs.16-19).

QUESTION:
Where do you want to be at such a time?

PRAYER:
Dear Lord, let our nation and leaders repent from all evil before Mercy ends, in Jesus' name, Amen.

Food for the Day - 2026

゚viralシalシ

31/07/2026

ỌJỌ́ ẸTÌ (FRIDAY),
31 JULY, 2026
Kíkọ Nínú Ìwé Orin ECWA: EHB 5
IBI KÍKÀ: ÌFIHÀN 8:6-13
KÓKÓ ẸKỌ: ÀWỌN ÌPÈ

ÌFIHÀN 8:6-13

6 Awọn angẹli meje na ti nwọn ni ipè meje si mura lati fun wọn.

7 Ekini si fun, yinyín ati iná ti o dàpọ̀ pẹlu ẹ̀jẹ si jade, a si dà wọn sori ilẹ aiye: idamẹta ilẹ aiye si jóna, idamẹta awọn igi si jóna, ati gbogbo koriko tutù si jóna.

8 Angẹli keji si fun, a si wọ́ ohun kan bi òke nla ti njona sọ sinu okun: idamẹta okun si di ẹ̀jẹ;

9 Ati idamẹta awọn ẹda ti mbẹ ninu okun ti o ni ẹmí si kú; ati idamẹta awọn ọkọ̀ si bajẹ.

10 Angẹli kẹta si fun, irawọ̀ nla kan ti njo bi fitila si bọ́ lati ọrun wá, o si bọ sori idamẹta awọn odo ṣiṣàn, ati sori awọn orisun omi;

11 A si npè orukọ irawọ na ni Iwọ idamẹta awọn omi si di iwọ, ọ̀pọlọpọ enia si ti ipa awọn omi na kú, nitoriti a sọ wọn di kikorò.

12 Angẹli kẹrin si fun, a si kọlu idamẹta õrùn, ati idamẹta oṣupa, ati idamẹta awọn irawọ, ki idamẹta wọn le ṣõkun, ki ọjọ maṣe mọlẹ fun idamẹta rẹ̀, ati oru bakanna.

13 Mo si wò, mo si gbọ́ idì kan ti nfò li ãrin ọrun, o nwi li ohùn rara pe, Egbé, egbé, egbé, fun awọn ti ngbe ori ilẹ aiye nitori ohùn ipè iyoku ti awọn angẹli mẹta ti mbọwá fun.

ÀWỌN ÌPÈ

Nínú ìwé Ìfihàn orí keje, a rí bí a tí fi ìpè (fèrè) fún àwọn áńgẹ́lì méje èyí tí ó se àpẹẹrẹ ìsẹ̀lẹ̀ orísirísi.

Ìpè (fèrè) tí áńgẹ́lì àkọ́kọ́ fọn mú ìdájọ́ wá, nígbà tí áńgẹ́lì kejì fọn ìpè tí ó yí òkè ńlá lọ sínú òkun, ẹ̀kẹta nínú àwọn áńgẹ́lì náà fọn ìpè (fèrè) èyí tí ó fa ìsubú ìràwọ̀ tí ńjò bí fitílà láti ọ̀run wá èyí tí ó sokùnfà kí ìdámẹ́ta àwọn odò sísàn àti àwọn orísun omi di kíkorò. Èyí tí ó fa kí apákan ìsẹ̀dá bájẹ́.

Ìpè (fèrè) tí áńgẹ́lì kẹrin fọn se àkọlù sí oòrùn, òsùpá àti ìràwọ̀,èyí tí ìkìlọ̀ ìparun ègbé sì tẹ̀lé fún gbogbo olùgbé orí ilẹ̀ ayé.

ÌBÉÈRÈ: Olúfẹ́, máṣe ronú láti kópa nínú ìpọ́njú ńlá náà

ÀDÚRÀ: Jésù Olúwa, fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ láti dúró nínú Rẹ títí di ìgbà tí màá fi ayé yí sílẹ̀, kí n ba à le bọ́ lọ́wọ́ ìpọ́nú ńlá yìí ní orúkọ Jésù, Àmín.

ÓÙNJẸ ÒÒJỌ́

Address

Behind Channel 7, Anglo-Jos
Anglo Jos

Website

Alerts

Be the first to know and let us send you an email when ECWA Church Anglo-Jos, Plateau State posts news and promotions. Your email address will not be used for any other purpose, and you can unsubscribe at any time.

Shortcuts

Share